< Psalms 60 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
Przewodnikowi chóru, n[a Sussanedut. Miktam Dawida dla pouczenia]; [gdy walczył przeciw Syryjczykom Nacharaim i przeciw Syryjczykom Soby, gdy Joab, wracając, pobił dwanaście tysięcy Edomitów w Dolinie Soli. ] Boże, odrzuciłeś nas, rozproszyłeś nas [i] rozgniewałeś się; powróć znowu do nas.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Wstrząsnąłeś ziemią i rozdarłeś ją; ulecz jej rozpadliny, bo się chwieje.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Okazywałeś twemu ludowi ciężkie rzeczy, napoiłeś nas winem odurzającym.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
Dałeś chorągiew tym, którzy się ciebie boją, aby wynieśli ją z powodu [twej] prawdy. (Sela)
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Aby byli ocaleni twoi umiłowani, wybaw [ich] swoją prawicą i wysłuchaj mnie.
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Bóg przemówił w swojej świętości; będę się radował, rozdzielę Sychem i wymierzę dolinę Sukkot.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
Mój [jest] Gilead, mój i Manasses, Efraim mocą mojej głowy, Juda moim prawodawcą.
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Moab moją misą do mycia, na Edom wrzucę mój but; Filisteo, wykrzykuj z mojego powodu.
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Kto mnie wprowadzi do miasta warownego? Kto mnie doprowadzi aż do Edomu?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Czy nie ty, o Boże, który nas odrzuciłeś i nie wychodziłeś, Boże, z naszymi wojskami?
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Udziel nam pomocy w utrapieniu, bo próżna jest pomoc ludzka.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
W Bogu będziemy mężni, bo on podepcze naszych nieprzyjaciół.

< Psalms 60 >