< Psalms 60 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
Przedniejszemu śpiewakowi na Sussanedut złota pieśń Dawidowa do nauczania; Gdy walczył przeciw Syryjczykom Nacharaim, i przeciw Syryjczykom Soby; gdy się wrócił Joab, poraziwszy Edomczyków w dolinie solnej dwanaście tysięcy. Boże! odrzuciłeś nas, rozproszyłeś nas, i rozgniewałeś się; nawróćże się zasię do nas.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Zatrząsnąłeś był ziemią, i rozsadziłeś ją; uleczże rozpadliny jej, boć się chwieje.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Okazywałeś ludowi twemu przykre rzeczy, napoiłeś nas winem zawrotu.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
Ale teraz dałeś chorągiew tym, którzy się ciebie boją, aby ją wynieśli dla prawdy twej. (Sela)
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Aby byli wybawieni umiłowani twoi; zachowajże ich prawicą twoją, a wysłuchaj mię.
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Bóg ci mówił w świętobliwości swojej; przeto się rozweselę, rozdzielę Sychem, i dolinę Sukkotską pomierzę.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
Mojeć jest Galaad, mój i Manases, i Efraim moc głowy mojej; Juda zakonodawcą moim.
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Moab miednicą do umywania mego; na Edoma wrzucę buty moje; ty, Palestyno! wykrzykaj nademną.
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Któż mię wprowadzi do miasta obronnego? kto mię przyprowadzi aż do Edom?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Izali nie ty, o Boże! któryś nas był odrzucił, a nie wychodziłeś, Boże! z wojskami naszemi?
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Dajże nam ratunek w utrapieniu; boć omylny ratunek ludzki.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
W Bogu mężnie sobie poczynać będziemy, a on podepcze nieprzyjaciół naszych.