< Psalms 60 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
Dāvida sirds dziesma. Dziedātāju vadonim, iemācīt pēc: „lilija ir liecība“; Kad viņš kāvās ar Sīriešiem no Mezopotamijas un ar Sīriešiem no Cobas, un Joabs nāca atpakaļ un sakāva no Edomiešiem divpadsmit tūkstošus sāls ielejā. Dievs, Tu mūs esi atmetis, izkaisījis, Tu esi bijis dusmīgs, griezies atkal pie mums.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Tu zemi esi kustinājis un šķēlis, dziedini viņas plīsumus, jo viņa šaubās.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Tu Saviem ļaudīm grūtumu esi licis redzēt, ar reibuma vīnu Tu mūs esi dzirdinājis.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
Tiem, kas Tevi bīstas, Tu esi devis karogu, celties patiesības labad. (Sela)
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Lai Tavi mīļie taptu atsvabināti, tad palīdzi nu ar Savu labo roku un paklausi mūs!
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Dievs runā Savā svētā vietā, par to es priecājos; es dalīšu Šehemi un mērošu Sukota ieleju.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
Gileāds Man pieder, un Manasus Man pieder, un Efraīms ir Manas galvas stiprums, Jūda ir Mans valdības zizlis.
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Moabs ir Mans mazgājamais trauks; Savu kāju Es stiepju pār Edomu; tu, Fīlistu zeme, kliedzi par Mani!
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Kas mani vadīs tai stiprā pilsētā? Kas mani pavadīs līdz Edomam?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Vai ne tu, Dievs, kas mūs biji atmetis un neizgāji, ak Dievs, ar mūsu karaspēku?
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Dod mums palīgu bēdu laikā, jo cilvēku pestīšana nav nekas.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
Ar Dievu darīsim stiprus darbus. Viņš samīdīs mūsu pretiniekus.

< Psalms 60 >