< Psalms 60 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
Þennan sálm orti Davíð þegar hann átti í ófriði við Sýrlendinga og óvíst var um úrslit. Þetta gerðist á sama tíma og Jóab, hershöfðingi Ísraels, vann sigur á 12.000 Edomítum í Saltdalnum. Þú Guð, hefur útskúfað okkur og brotið niður varnirnar. Þú hefur reiðst okkur og tvístrað. Drottinn sýndu aftur miskunn þína.
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
Þú lést landið skjálfa, sprungur opnuðust. Drottinn læknaðu það og græddu sárin.
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
Þú lést lýð þinn kenna á hörðu, við reikuðum eins og drukknir menn.
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
En nú hefur þú reist okkur herfána! Þangað stefnum við allir sem elskum þig.
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Réttu út þína sterku hönd og frelsaðu okkur! Bjargaðu ástvinum þínum.
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
Guð hefur heitið hjálp. Hann hefur svarið það við heilagleika sinn! Er að undra þótt ég sé glaður?!
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
„Síkem, Súkkót, Gíleað, Manasse – allt er þetta mitt, “segir hann. „Júda gefur konung og Efraím varðmenn.
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
Móab er þjónn minn og Edóm þræll. Og yfir Filisteu æpi ég siguróp!“
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
Hver fer með til Edóms, inn í víggirtar borgir hans?
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
Guð! Hann sem áður útskúfaði og yfirgaf hersveitir okkar!
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
Drottinn, styð okkur gegn óvinunum, því að ekki hjálpa menn.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
Með Guðs hjálp vinnum við stórvirki, hann mun fótum troða óvinina.