< Psalms 60 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Lílì ti Májẹ̀mú.” Miktamu ti Dafidi. Fún ìkọ́ni. Nígbà tí ó bá Aramu-Naharaimu àti Siria-Soba jà, àti nígbà tí Joabu yípadà tí ó sì pa ẹgbẹ̀rún méjìlá àwọn ará Edomu ní àfonífojì Iyọ̀. Ìwọ ti kọ̀ wá sílẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ ti tú wa ká, ìwọ ti bínú nísinsin yìí, tún ara rẹ yípadà sí wa.
[I prayed], “God, you have rejected us [Israelis]! Because you have been angry [with us], you have [enabled our enemies] to break through our ranks. [Please] enable us to be strong again!
2 Ìwọ ti mú ilẹ̀ wárìrì, ìwọ ti fọ́ ọ; mú fífọ́ rẹ̀ bọ̀ sípò, nítorí tí ó mì.
[When we were defeated, it was as though] [MET] there was a big earthquake in our land that caused the ground to split open. So now, [just as only you can] cause the cracks in the land to disappear, [help our army to be strong again], because [it is as though] our country is (falling apart/being destroyed).
3 Ìwọ ti fi ìgbà ewu han àwọn ènìyàn rẹ; ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wá gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
You have caused [us], your people, to suffer very much; [it is as though] you forced us to drink [strong] wine that caused us to stagger around [after we became drunk].
4 Àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, ní ìwọ fi ọ̀págun fún kí a lè fihàn nítorí òtítọ́. (Sela)
But you have raised a battle flag for those who revere you in order that they can gather around it and not [be killed by the enemies’] arrows.
5 Fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbà wá, kí o sì ràn wá lọ́wọ́, kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.
Answer our [prayers] and enable us by your power [MTY] to defeat [our enemies] in order that we, the people whom you love, will be saved.”
6 Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀: “Ní ayọ̀, èmi ó pọ Ṣekemu jáde èmi ó sì wọ́n àfonífojì Sukkoti.
[Then] God [answered my prayer and] spoke from his temple, saying, “Because I have conquered [your enemies], I will divide up [everything in] Shechem [city], and I will distribute it among my people [the land in] Succoth Valley.
7 Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase; Efraimu ni àṣíborí mi, Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.
The Gilead [region] is mine; the [people of the tribe of] Manasseh are mine; [the tribe of] Ephraim is [like] my helmet [MET]; and [the tribe of] Judah is [like] the (scepter/stick [that I hold which shows that I am the ruler]) [MET];
8 Moabu ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ní mo bọ́ bàtà mi sí; lórí Filistia ni mo kígbe ayọ̀.”
but the Moab [region] is [like] my washbasin [MET]; I throw my sandal in the Edom [area to show that it belongs to me]; I shout triumphantly because I have defeated [the people of] the Philistia [area].”
9 Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì? Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Edomu?
[Because I want to defeat the people of] Edom, (who will lead my [army triumphantly] to their [capital] city that has strong walls around it?/I want someone to lead my [army triumphantly] to their [capital] city that has strong walls around it.)” [RHQ]
10 Kì í ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀ tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?
So, God, we [desire/hope that] [RHQ] you have not truly abandoned us, and that you will go with us when our armies march out [to fight our enemies].
11 Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá, nítorí asán ni ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.
[We need you to] help us when we fight against our enemies, because the help that humans can give us is worthless.
12 Nípa Ọlọ́run ni a óò ní ìṣẹ́gun, yóò sì tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.
But with you [helping us], we shall win; you will enable us to defeat our enemies.

< Psalms 60 >