< Psalms 6 >
1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
Para o músico chefe; sobre instrumentos de corda, sobre a lira de oito cordas. Um salmo de David. Yahweh, não me repreenda com sua raiva, nem me disciplinam em sua ira.
2 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
Tenha piedade de mim, Yahweh, pois estou desmaiado. Yahweh, cura-me, pois meus ossos estão perturbados.
3 Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
Minha alma também está em grande angústia. Mas você, Yahweh, quanto tempo?
4 Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
Return, Yahweh. Entregue minha alma, e me salve por sua amorosa bondade.
5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol )
Pois na morte não há memória de você. No Sheol, quem lhe agradecerá? (Sheol )
6 Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
Estou cansado com meu gemido. Todas as noites eu inunda minha cama. Eu molho meu sofá com minhas lágrimas.
7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
Meu olho se esgota por causa da dor. Ela envelhece por causa de todos os meus adversários.
8 Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
Depart de mim, todos vocês trabalhadores da iniqüidade, pois Yahweh ouviu a voz do meu choro.
9 Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
Yahweh ouviu minha súplica. Yahweh aceita minha oração.
10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
Que todos os meus inimigos se envergonhem e fiquem consternados. Eles devem voltar para trás, devem ser desonrados de repente.