< Psalms 6 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
برای رهبر سرایندگان: مزمور داوود، با همراهی سازهای زهی، در مایۀ شِمینیت. ای خداوند، مرا در شدت خشم خود توبیخ و تنبیه نکن.
2 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
ای خداوند، به من رحم کن زیرا پژمرده شده‌ام. خداوندا، مرا شفا ده، زیرا دردْ وجودم را فرا گرفته
3 Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
و بسیار پریشانم. تا به کی ای خداوند، تا به کی؟
4 Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
ای خداوند، بیا و مرا برهان؛ به خاطر محبت خود، مرا نجات ده.
5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol h7585)
زیرا مردگان نمی‌توانند تو را به یاد آورند. کیست که در قبر تو را ستایش کند؟ (Sheol h7585)
6 Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
از نالیدن خسته شده‌ام. هر شب بسترم را غرق اشک می‌سازم.
7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
از آزار دشمنانم آنقدر گریه کرده‌ام که چشمانم تار شده‌اند.
8 Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
ای همهٔ بدکاران، از من دور شوید؛ زیرا خداوند صدای گریهٔ مرا شنیده است.
9 Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
او به فریاد من خواهد رسید و دعایم را اجابت خواهد کرد.
10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
آنگاه همهٔ دشمنانم ناگهان عاجز و درمانده شده، با سرافکندگی دور خواهند شد.

< Psalms 6 >