< Psalms 6 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
Ki te tino kaiwhakatangi Nekinoto, he mea Heminiti. He himene na Rawiri. E Ihowa, kaua e whakatupehupehu mai ki ahau, ina riri koe, kaua ano ahau e pakia ina arita mai koe.
2 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
E Ihowa, tohungia ahau, he ngoikore hoki ahau: rongoatia ahau, e Ihowa, e ohooho ana hoki oku wheua.
3 Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
E ohooho noa iho ana hoki toku wairua: ko koe ia, e Ihowa, kia pehea atu te roa?
4 Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
Hoki mai, e Ihowa, kia mawhiti atu toku wairua: kia mahara ki tou aroha, a whakaorangia ahau.
5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol h7585)
Kahore hoki he mahara ki a koe ina mate: ko wai hei whakawhetai ki a koe i roto i te reinga? (Sheol h7585)
6 Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
Mauiui iho ahau i toku auetanga; e manu ana toku moenga i ahau a pau noa te po; e whakamakukuria ana e ahau toku takotoranga ki oku roimata.
7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
Pakoko kau toku kanohi i te tangi; kua koroheke haere i oku hoariri katoa.
8 Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
Mawehe atu i ahau, e nga kaimahi katoa i te kino; kua rongo nei hoki a Ihowa i te reo o taku tangi.
9 Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
Kua rongo a Ihowa ki taku inoi; ka manako a Ihowa ki taku karakia.
10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
Ka whakama, ka pokaikaha noa iho oku hoariri katoa: ka hoki ratou, ka pa whakarere atu te whakama.

< Psalms 6 >