< Psalms 6 >
1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
Au maître de chant. Sur les instruments à cordes. À l’octave. Psaume de David. Yahweh, ne me punis pas dans ta colère, et ne me châtie pas dans ta fureur.
2 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
Aie pitié de moi, Yahweh, car je suis sans force; guéris-moi, Yahweh, car mes os sont tremblants.
3 Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
Mon âme est dans un trouble extrême; et toi, Yahweh, jusques à quand…?
4 Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
Reviens, Yahweh, délivre mon âme; sauve-moi à cause de ta miséricorde.
5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol )
Car celui qui meurt n’a plus souvenir de toi; qui te louera dans le schéol? (Sheol )
6 Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
Je suis épuisé à force de gémir; chaque nuit ma couche est baignée de mes larmes, mon lit est arrosé de mes pleurs.
7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
mon œil est consumé par le chagrin; il a vieilli à cause de tous ceux qui me persécutent.
8 Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
Éloignez-vous de moi, vous tous qui faites le mal!
9 Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
Yahweh a entendu ma supplication, Yahweh accueille ma prière.
10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
Tous mes ennemis seront confondus et saisis d’épouvante; ils reculeront, soudain couverts de honte.