< Psalms 6 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin olókùn. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Olúwa, má ṣe bá mi wí nínú ìbínú rẹ kí ìwọ má ṣe nà mí nínú gbígbóná ìrunú rẹ.
O Yhwh, rebuke me not in thine anger, neither chasten me in thy hot displeasure.
2 Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń kú lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.
Have mercy upon me, O Yhwh; for I am weak: O Yhwh, heal me; for my bones are vexed.
3 Ọkàn mi wà nínú ìrora. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?
My soul is also sore vexed: but thou, O Yhwh, how long?
4 Yípadà, Olúwa, kí o sì gbà mí; gbà mí là nípa ìfẹ́ rẹ tí kì í ṣákì í.
Return, O Yhwh, deliver my soul: oh save me for thy mercies’ sake.
5 Ẹnikẹ́ni kò ni rántí rẹ nígbà tí ó bá kú. Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú isà òkú? (Sheol h7585)
For in death there is no remembrance of thee: in the grave who shall give thee thanks? (Sheol h7585)
6 Agara ìkérora mi dá mi tán. Gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkún, mo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.
I am weary with my groaning; all the night make I my bed to swim; I water my couch with my tears.
7 Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́; wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.
Mine eye is consumed because of grief; it waxeth old because of all mine enemies.
8 Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi, nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.
Depart from me, all ye workers of iniquity; for Yhwh hath heard the voice of my weeping.
9 Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.
Yhwh hath heard my supplication; Yhwh will receive my prayer.
10 Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú; wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.
Let all mine enemies be ashamed and sore vexed: let them return and be ashamed suddenly.

< Psalms 6 >