< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Nkunga Davidi kuidi pfumu minyimbidi “Kadi vonda” mu thangu Sawuli kafidisa batu bazungidila nzo Davidi mu diambu bamvonda. Wukhula mu bambeni ziama, a Nzambi; wukhebi mu diambu bobo bamfuemini!
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Wukhudi mu mimvangi mi mambimbi ayi wuphukisa mu mintengudi mi menga.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Tala phila balambididi mu kuphingila. Batu badi ngolo bandiendidi manenga bika sia ti mu diambu di nzimbala yama voti mu diambu di disumu diama, a Nzambi.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Kadi mbimbi ndisia vanga ko vayi bakubimini mu kunduanisa kotuka mu kutsadisa tala phila ndikila.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
A Yave, Nzambi nkua ngolo yoso, Nzambi yi Iseli, kotuka mu tumbudila makanda moso; kadi mona kadi kiadi kuidi bobo beti vanga mambimbi.
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Bamvutukanga va masika, beti lola banga zimbua; ayi beti zungidila divula.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Tala, momo balembo luki mu miunu miawu. Bisabala bidi mu bididi biawu. Ayi balembo tubi: “Nani wulenda kutu wa e?”
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Vayi ngeyo, a Yave, wulenda basevi; wulembo sekinina makanda moso momo.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
E ngolo ziama, kuidi ngeyo ndintala, ngeyo, e Nzambi, widi tinunu kiama ki ngolo.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Nzambi ama, wukuphangilanga mamboti Nzambi ama yi luzolo wela kundengana; Nzambi wela diata va ntuala ama ayi wela kumbonisa khini vadi bobo bakuthubidilanga.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Vayi kadi kuba vonda, a Yave, nkaku eto, bila muna batu bama bela zimbakana. Mu lulendo luaku, baba mindiengidi ayi wuba buisi.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Mu diambu di masumu ma muinu miawu, mu diambu di mambu ma bididi biawu, bika babuilama mu luniemo luawu. Mu diambu di zitsingulu ayi luvunu beti totula,
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Wuba lalikisa mu nganzi aku yi kikhesa; wuba lalikisa muingi babika buela monika buna diela zabakana mu zitsuka zi ntoto ti Nzambi wunyadila Yakobi.
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
Bamvutukanga va masika, beti lola banga zimbua, ayi beti zungidila divula.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Bandiengilanga mu diambu di bidia, ayi enati bakadi yukuta, buna banyamikinanga.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Vayi minu, ndiela yimbidila zingolo ziaku; muna nsuka, ndiela yimbidila luzolo luaku bila ngeyo tinunu kiama kingolo ayi suamunu mu zithangu zi ziphasi.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
A ngeyo zingolo ziama, ndinyimbila nzitusu mu diambu diaku; ngeyo Nzambi, ngeyo tinunu kiama kingolo; Nzambi ama yi luzolo.

< Psalms 59 >