< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Керівнику хору. На мотив «Не згуби». Міхтам Давидів, коли Саул послав людей стерегти його дім, щоб убити його. Визволи мене від ворогів Моїх, Боже мій, захисти мене від тих, хто підноситься проти мене.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Від тих, що чинять беззаконня, визволи мене і від людей кровожерних врятуй мене.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Ось вони чатують на душу мою, сильні змовляються проти мене не за беззаконня моє чи гріх, Господи.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Немає беззаконня в мене, але збігаються вони й готуються [до нападу]. Піднімися назустріч мені й поглянь.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ти, Господи, Боже Воїнств, Боже Ізраїлю, пробудися, щоб покарати всі народи; не помилуй жодного з нечестивих зрадників! (Села)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Вони повертаються в сутінках вечірніх, виють, немов пси, обступають місто звідусіль.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Ось вивергають вони ганьбу, в устах у них – мечі! На їхніх язиках [приказка]: «Хто чує?»
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Але Ти, Господи, посмієшся з них, поглузуєш з усіх народів.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Сило моя, Тебе я пильную очікуючи, адже Ти, Боже, твердиня моя.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Бог, Що милує мене, піде поперед мене [переможно]; Бог покаже мені [падіння] супротивників моїх.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Не вбивай їх, щоб не забув мій народ; розкидай їх силою Своєю і кинь їх долілиць, щите наш, Владико!
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Гріх вуст їхніх – це слова, що губи їхні [промовили]. Нехай впіймані вони будуть гординею своєю за прокляття й кривду, що вони розповсюджують.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Знищ їх у гніві, знищ, щоб не було їх! Тоді відомо стане аж до країв землі, що Бог володарює серед Якова. (Села)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
А вони повертаються в сутінках вечірніх, виють, немов пси, обступають місто звідусіль. (Села)
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Вони вештаються в пошуках їжі, та, не наситившись, ночують.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
А я буду співати про міць Твою і вранці радісно про милість Твою виспівувати. Адже Ти був для мене прихистком, притулком у день моєї скорботи.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
Сило моя, Тобі я співатиму, адже Ти, Боже, твердиня моя, Бог, Який милує мене.

< Psalms 59 >