< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Думнезеуле, скапэ-мэ де врэжмаший мей, окротеште-мэ де потривничий мей!
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Скапэ-мэ де рэуфэкэторь, избэвеште-мэ де оамений сетошь де сынӂе!
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Кэч ятэ-й кэ стау ла пындэ сэ-мь я вяца; ниште оамень порниць ла рэу урзеск лукрурь реле ымпотрива мя, фэрэ сэ фиу виноват, фэрэ сэ фи пэкэтуит, Доамне!
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Ку тоатэ невиновэция мя, ей аляргэ, се прегэтеск: трезеште-Те, ешь ынаинтя мя ши привеште!
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Доамне, Думнезеул оштирилор, Думнезеул луй Исраел, скоалэ-Те, ка сэ педепсешть тоате нямуриле! Н-авя милэ де ничунул дин ачешть вынзэторь нелеӂюиць!
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Се ынторк ын фиекаре сярэ, урлэ ка ниште кынь ши дау окол четэций.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Да, дин гура лор цышнеште рэул, пе бузеле лор сунт сэбий, кэч зик: „Чине ауде?”
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Дар Ту, Доамне, рызь де ей, Ту Ыць баць жок де тоате нямуриле.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Орькаре ле-ар фи путеря, еу ын Тине нэдэждуеск, кэч Думнезеу есте скэпаря мя.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Думнезеул меу, ын бунэтатя Луй, ымь есе ынаинте, Думнезеу мэ фаче сэ-мь вэд ымплинитэ доринца фацэ де чей че мэ пригонеск.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Ну-й учиде, ка сэ ну уйте лукрул ачеста попорул меу, чи фэ-й сэ прибеӂяскэ, прин путеря Та, ши добоарэ-й, Доамне, Скутул ностру!
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Гура лор пэкэтуеште ла фиекаре ворбэ каре ле есе де пе бузе: сэ се приндэ ын ынсэшь мындрия лор, кэч ну спун декыт блестеме ши минчунь!
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Нимичеште-й ын мыния Та, прэпэдеште-й ка сэ ну май фие! Фэ-й сэ штие кэ ымпэрэцеште Думнезеу песте Иаков, пынэ ла марӂиниле пэмынтулуй!
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
Се ынторк ын фиекаре сярэ, урлэ ка ниште кынь ши дау окол четэций.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Умблэ ынкоаче ши ынколо дупэ хранэ ши петрек ноаптя несэтуй.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Дар еу вой кынта путеря Та; дис-де-диминяцэ, вой лэуда бунэтатя Та. Кэч Ту ешть ун турн де скэпаре пентру мине, ун лок де адэпост ын зиуа неказулуй меу.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
О, Тэрия мя! Пе Тине Те вой лэуда, кэч Думнезеу, Думнезеул меу чел пря бун, есте турнул меу де скэпаре.

< Psalms 59 >