< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Przedniejszemu śpiewakowi, jako: Nie zatracaj, złota pieśń Dawidowa, gdy posłał Saul, aby strzeżono domu jego, a zabito go. Wyrwij mię od nieprzyjaciół moich, o Boże mój! a od powstawających przeciwko mnie uczyń mię bezpiecznym.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Wyrwij mię od tych, którzy broją nieprawość, a od mężów krwawych wybaw mię.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Albowiem oto czyhają na duszę moję; zbierają się przeciwko mnie mocarze bez przestępstwa mego i bez grzechu mego, o Panie!
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Bez wszelkiej nieprawości mojej zbiegają się, i gotują się; powstańże, zabież mi, a obacz.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ty sam, Panie, Boże zastępów, Boże Izraelski! ocuć się, abyś nawiedził te wszystkie narody; a nie miej litości nad żadnym z onych przestępców złośliwych. (Sela)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Nawracają się pod wieczór, a warczą jako psy, i biegają około miasta.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Oto blegocą usty swemi, miecze są w wargach ich; albowiem mówią: Któż słyszy?
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Ale ty, Panie! naśmiewasz się z nich; naśmiewasz się ze wszystkich narodów.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Gdy on moc przewodzi, na ciebie pozór mieć będę; boś ty, Boże! twierdzą moją.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Bóg mój miłosierny uprzedzi mię; Bóg mi da oglądać pomstę nad nieprzyjaciółmi mymi.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Nie zabijajże ich, aby nie zapomniał lud mój; ale ich rozprosz mocą twoją, i zrzuć ich, tarczo nasza, o Panie!
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Grzech ust swych, słowa warg swych (pojmani będąc w hardości swej dla złorzeczeństwa i kłamstwa) niech wyznawają.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Wytraćże ich w popędliwości, wytrać ich, aż ich nie stanie. Niech poznają, że Bóg panuje w Jakóbie, i po krajach ziemi. (Sela)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
I niech się zaś nawrócą pod wieczór; niech warczą jako psy, a biegają około miasta.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Niech oni ciekają, chcąc się najeść, wszakże głodni będąc ukłaść się muszą.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Ale ja będę śpiewał o mocy twojej; zaraz z poranku wysławiać będę miłosierdzie twoje; boś ty był twierdzą moją, i ucieczką w dzień ucisku mego.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
O mocy moja! tobie będę śpiewał; boś ty, Boże! twierdza moja, Bóg mój miłosierny.

< Psalms 59 >