< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Ki te tino kaiwhakatangi. Aratakiti. He Mikitama na Rawiri, i a Haora i tono tangata hei tiaki mo te whare, hei whakamate mona. Whakaorangia ahau, e toku Atua, i oku hoariri: whakateiteitia ake ahau i te hunga e whakatika ana ki ahau.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Whakaorangia ahau i nga kaimahi i te kino: kia ora ahau i te hunga toto.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Kei te whanga nei hoki ratou mo toku wairua: e whakamine ana te hunga kaha ki te whawhai ki ahau; kahore nei oku tutu, kahore oku hara, e Ihowa.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Hore oku kino, oma ana ratou, kei te takatu: e ara hei awhina moku, titiro mai hoki.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ae ra, maranga, e Ihowa, e te Atua o nga mano, e te Atua o Iharaira, tirohia iho nga tauiwi katoa: kaua e tohungia tetahi o te hunga kino, e poka ke nei. (Hera)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Ka hoki mai ratou i te ahiahi, kei te tau, ano he kuri, taiawhiotia ana e ratou te pa.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Nana, kei te kupa o ratou mangai, he hoari kei o ratou ngutu: ki ta ratou, ko wai e rongo?
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Ko tau ia, e Ihowa, he kata ki a ratou: hei tawainga mau nga tauiwi katoa.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
E toku kaha, ka tatari ahau ki a koe: ko te Atua hoki toku pa.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Kei mua i ahau toku Atua aroha: ma te Atua ahau ka kite i taku i hiahia ai ki oku hoariri.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Kaua ratou e whakamatea, kei wareware toku iwi: kia whakamararatia ratou e tou kaha; whakataka iho ratou, e te Ariki, e to matou whakangungu rakau.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Mo te hara o to ratou mangai, mo nga kupu a o ratou ngutu, hopukia ratou i runga i to ratou whakakake, mo ta ratou korero, he kanga, he teka.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Whakamotitia i runga i te riri, kia kahore ai ratou: a kia matau ratou ko te Atua te Kawana o Hakopa puta noa ki nga pito o te whenua. (Hera)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
I te ahiahi tukua ratou kia hoki, tukua ratou kia tau, ano he kuri, kia taiawhio ratou i te pa.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Ka kopikopiko noa ratou ki te rapu kai, a ka tauwhanga i te po roa ina kore ratou e makona.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Ko ahau ia, ka waiatatia e ahau tou kaha; ae, i te ata ka hamamatia e ahau tau mahi toku: ko koe hoki toku pa, toku piringa i te ra o toku pouri.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
Ka himene ahau ki a koe, e toku kaha: ko te Atua nei hoki toku pa, toku Atua aroha.

< Psalms 59 >