< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Pour le chef musicien. Sur l'air de « Do Not Destroy ». Un poème de David, quand Saul a envoyé, et ils ont regardé la maison pour le tuer. Délivre-moi de mes ennemis, mon Dieu. Mettez-moi à l'abri de ceux qui s'élèvent contre moi.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Délivre-moi des ouvriers de l'iniquité. Sauve-moi des hommes assoiffés de sang.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Car voici, ils sont aux aguets pour mon âme. Les puissants s'assemblent contre moi, pas pour ma désobéissance, ni pour mon péché, Yahvé.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Je n'ai rien fait de mal, mais ils sont prêts à m'attaquer. Lève-toi, regarde, et aide-moi!
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Toi, Yahvé, Dieu des armées, le Dieu d'Israël, réveillez-vous pour punir les nations. N'ayez aucune pitié pour les méchants traîtres. (Selah)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Ils reviennent le soir, en hurlant comme des chiens, et rôdent dans la ville.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Voici, ils crachent de leur bouche. Les épées sont dans leurs lèvres, « Car », disent-ils, « qui nous entend? »
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Mais toi, Yahvé, tu te moques d'eux. Vous vous moquez de toutes les nations.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Oh, ma force, je veille sur toi, car Dieu est ma haute tour.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Mon Dieu marchera devant moi avec sa bonté. Dieu me permettra de regarder mes ennemis en triomphe.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Ne les tue pas, sinon mon peuple pourrait oublier. Disperse-les par ta puissance, et fais-les tomber, Seigneur notre bouclier.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
A cause du péché de leur bouche, et des paroles de leurs lèvres, qu'ils soient pris dans leur orgueil, pour les malédictions et les mensonges qu'ils profèrent.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Consommez-les dans la colère. Consommez-les, et ils ne seront plus. Faites-leur savoir que Dieu règne sur Jacob, jusqu'aux extrémités de la terre. (Selah)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
Le soir, qu'ils reviennent. Laissez-les hurler comme un chien, et faire le tour de la ville.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Ils erreront de long en large pour trouver de la nourriture, et attendre toute la nuit s'ils ne sont pas satisfaits.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Mais je chanterai ta force. Oui, je chanterai à haute voix ta bonté au matin. Car tu as été ma haute tour, un refuge au jour de ma détresse.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
A toi, ma force, je chanterai des louanges. Car Dieu est ma haute tour, le Dieu de ma miséricorde.

< Psalms 59 >