< Psalms 59 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Veisuunjohtajalle; veisataan kuin: "Älä turmele"; Daavidin laulu, kun Saul lähetti vartioimaan hänen taloansa, tappaakseen hänet. Jumalani, pelasta minut vihollisistani, suojele minua niiltä, jotka nousevat minua vastaan.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Pelasta minut pahantekijöistä, vapahda minut murhamiehistä.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Sillä katso, he väijyvät minun henkeäni; julmurit kokoontuvat minua vastaan, vaikka en ole rikkonut enkä syntiä tehnyt, Herra.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Ilman minun syytäni he juoksevat ja hankkiutuvat; heräjä, käy minua kohtaamaan ja katso.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ja sinä, Herra, Jumala Sebaot, Israelin Jumala, heräjä kostamaan kaikille pakanoille. Älä säästä ketään uskotonta väärintekijää. (Sela)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
He tulevat ehtoolla, ulvovat kuin koirat ja kiertävät kaupunkia.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Katso, he purkavat suustaan sisuansa, miekat ovat heidän huulillansa, sillä: "Kuka sen kuulee?"
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Mutta sinä, Herra, naurat heille, sinä pidät kaikkia pakanoita pilkkanasi.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Sinä, minun väkevyyteni, sinusta minä otan vaarin, sillä Jumala on minun linnani.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Minun armollinen Jumalani käy minua kohden, Jumala antaa minun nähdä iloni vihollisistani.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Älä heitä tapa, ettei minun kansani sitä unhottaisi. Saata voimallasi heidät harhailemaan ja syökse heidät maahan, Herra, meidän kilpemme.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Minkä he huulillaan puhuvat, sen he suullaan syntiä tekevät. Joutukoot he ylpeydessään kiinni kirousten ja valheiden tähden, joita he puhuvat.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Hävitä heidät vihassasi, hävitä olemattomiin, ja tietäkööt he, että Jumala hallitsee Jaakobissa, maan ääriin saakka. (Sela)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
He tulevat ehtoolla, ulvovat kuin koirat ja kiertävät kaupunkia.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
He harhailevat ruuan haussa; elleivät tule ravituiksi, he murisevat.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Mutta minä veisaan sinun väkevyydestäsi ja riemuitsen aamulla sinun armostasi, sillä sinä olet minun linnani ja pakopaikkani minun hätäni päivänä.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
Sinä, minun väkevyyteni, sinulle minä veisaan kiitosta, sillä Jumala on minun linnani ja minun armollinen Jumalani.