< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
Davidin kultainen kappale, ettei hän hukkunut, kuin Saul lähetti hänen huonettansa piirittämään, saadaksensa häntä tappaa. Pelasta minua vihollisistani, Jumala, ja varjele minua niistä, jotka itseänsä asettavat minua vastaan.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Pelasta minua pahointekiöistä, ja auta minua murhamiehistä;
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Sillä katso, Herra, he väijyvät sieluani: väkevät kokoontuvat minua vastaan, ilman minun syytäni ja rikostani.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
He juoksevat ilman syytä, ja valmistavat itseänsä: nouse tulemaan minua vastaan ja katsomaan.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ja sinä, Herra Jumala Zebaot, Israelin Jumala, herää etsimään kaikkia pakanoita: älä ketään heistä armahda, jotka niin väkivaltaisesti vääryyttä tekevät, (Sela)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
He tulkoon taas ehtoona, ja ulvokaan niinkuin koira, ja samotkaan ympäri kaupungin.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Katso, he puhuvat suullansa: miekat ovat heidän huulissansa, kuka sen kuulis.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Mutta sinä, Herra, naurat heitä, ja pilkkaat kaikkia pakanoita.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
Heidän väkevyytensä edestä minä turvaan sinun tykös; sillä Jumala on minun varjelukseni.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Jumala osoittaa minulle runsaasti laupiutensa, Jumala antaa minun nähdä koston vihollisistani.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Älä heitä tapa, ettei minun kansani sitä unohtaisi: hajoita heitä voimallas, ja lyö heitä maahan, Herra meidän kilpemme.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Heidän huultensa puhe on heidän suunsa synti: ja he käsitetään ylpeydessänsä: ja he juttelevat kirouksia ja valhetta.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Pyyhi heitä pois vihassas, pyyhi heitä pois, ettei he olisikaan; että he ymmärtäisivät sen, että Jumala hallitsee Jakobissa, hamaan maailman ääriin asti, (Sela)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
He tulkoon taas ehtoona, ja ulvokaan niinkuin koira, ja samotkaan ympäri kaupungin.
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Anna heidän juosta sinne ja tänne ruoan tähden; ja ulvokaan, koska ei he ravituksi tule.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
Mutta minä veisaan sinun väkevyyttäs, ja varhain kerskaan sinun laupiuttas; sillä sinä olet minun varjelukseni ja turvani minun hädässäni.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
Sinä olet minun väkevyyteni, sinulle minä kiitosta veisaan; sillä sinä Jumala olet minun varjelukseni ja minun armollinen Jumalani.

< Psalms 59 >