< Psalms 59 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí Saulu rán àwọn olùṣọ́ sí ilé Dafidi kí òun bá le rí i pa. Gbà mí lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá à mi, Ọlọ́run; dáàbò bò mí kúrò lọ́dọ̀ àwọn tí ó dìde sí mi.
За първия певец, по Не Разорявай. Песен на Давида, когато Саул прати стражи да пазят къщата, в която бе Давид, за да го убият. Избави ме от неприятелите ми, Боже мой; Тури ме на високо от ония, които се повдигат против мене.
2 Gbà mí lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ búburú kí o sì gbà mí lọ́wọ́ àwọn ènìyàn tí ń pòǹgbẹ ẹ̀jẹ̀.
Избави ме от ония, които вършат беззаконие, И спаси ме от кръвопийци.
3 Wò ó, bí wọ́n ṣe ba ní bùba dè mí! Àwọn alágbára ń gbìmọ̀ lòdì sí mi kì í ṣe nítorí ìrékọjá mi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ mí, Olúwa.
Защото, ето, причакват за да уловят душата ми; Силните се събират против мене, Не за мое престъпление, Господи, нито за мой грях.
4 Èmi kò ṣe àìṣedéédéé kan, síbẹ̀ wọ́n sáré wọ́n ṣetán láti kọlù mí. Dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi, kí o sì wo àìlera mi.
Без да има в мене вина тичат и се готвят; Събуди се да ме посрещнеш и виж.
5 Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli, dìde fún ara rẹ kí o sì bá àwọn orílẹ̀-èdè wí; má ṣe ṣàánú fún àwọn olùrékọjá búburú nì. (Sela)
Ти, Господи Боже на силите, Боже Израилев, Стани за да посетиш всички народи; Да не покажеш милост към никого от нечестивите престъпници. (Села)
6 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọ́n ń gbó bí àwọn ajá, wọ́n ń rìn yí ìlú náà káàkiri.
Вечер се връщат, Вият като кучета и обикалят града.
7 Kíyèsi ohun tí wọ́n tú jáde ní ẹnu: wọn ń tú idà jáde láti ètè wọn, wọ́n sì wí pé, “Ta ni ó lè gbọ́ ọ̀rọ̀ wa?”
Ето, те бълват думи с устата си; Мечове има в устните им, Понеже, думат те: Кой слуша?
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, yóò fi wọ́n rẹ́rìn-ín, Ìwọ ó yọ ṣùtì sí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè.
Но, Ти Господи, ще им се присмееш, Ще се поругаеш на всички тия народи.
9 Ìwọ agbára mi, èmi ó máa kọrin ìyìn sí ọ; nítorí ìwọ Ọlọ́run ni ààbò mi,
О Сило моя, на Тебе ще се надея. Защото Бог ми е крепост.
10 Ọlọ́run àánú mi ni yóò ṣáájú mi. Ọlọ́run yóò sì jẹ́ kí èmi rí ìfẹ́ mi lára àwọn ọ̀tá mi. Yóò sì jẹ́ kí n yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi.
Милостивият мой Бог ще ме предвари; Бог ще ме удостои да видя повалянето на ония, които ме причакват.
11 Ṣùgbọ́n má ṣe pa wọ́n, Olúwa asà wa, kí àwọn ènìyàn mi má ba à gbàgbé. Nínú agbára rẹ, jẹ́ kí wọn máa rìn kiri, kí o sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.
Да ги не убиеш, да не би да забравят това моите люде; Разпръсни ги със силата Си. И свели ги, Господи, защитниче наш.
12 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ẹnu wọn, ní ọ̀rọ̀ ètè wọn, kí a mú wọn nínú ìgbéraga wọn. Nítorí èébú àti èké tí wọn ń sọ,
Поради греха на устата си, поради думите на устните си, Нека бъдат уловени в гордостта си, Също и поради клетвата и лъжата що говорят.
13 pa wọ́n run nínú ìbínú, run wọ́n di ìgbà tí wọn kò ní sí mọ́. Nígbà náà ni yóò di mí mọ̀ dé òpin ayé pé Ọlọ́run jẹ ọba lórí Jakọbu. (Sela)
Довърши го с гняв, довърши ги да ги няма вече, И нека се научат, че Бог господарува в Якова И до краищата на земята. (Села)
14 Wọ́n padà ní àṣálẹ́, wọn ń gbó bí àwọn ajá wọ́n ń rin ìlú náà káàkiri.
Нека се връщат вечер, Нека вият като кучета, и нека обикалят града;
15 Wọ́n ń rin kiri fún oúnjẹ wọ́n sì ń yán nígbà tí wọn kò yó.
Нека се скитат за храна; И ако не се настанят, нека прекарат нощта не наситени.
16 Ṣùgbọ́n èmi ó kọrin agbára rẹ, n ó kọrin ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀; nítorí ìwọ ni ààbò mi, ibi ìsádi mi ní ìgbà ìpọ́njú.
А аз ще пия за Твоята сила, Да! на ранина високо ще славословя Твоята милост; Защото Ти си ме станал крепост И прибежище в деня на бедствието ми.
17 Ìwọ agbára mi, èmi ó kọrin ìyìn sí ọ; ìwọ, Ọlọ́run, ààbò mi, Ọlọ́run ìfẹ́ mi.
О Сило моя, на Тебе ще пея хваление. Защото Ти, Боже, милостиви мой Бог, Си крепост моя.

< Psalms 59 >