< Psalms 58 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́ ẹ̀yin ìjọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
Þið konungar og leiðtogar þjóðanna, talið þið sannleika? Er réttlæti í dómum ykkar og úrskurðum?
2 Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo, ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
Nei, svo er ekki. Þið eruð allir svikarar sem seljið „réttlæti“fyrir mútur.
3 Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà, lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
Slíkir menn hafa allt frá fæðingu vikið af réttum vegi. Þeir hafa talað lygi frá því þeir fengu málið.
4 Oró wọn dàbí oró ejò, wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
Eiturnöðrur eru þeir, slöngur sem daufheyrast við skipunum særingamannsins.
5 tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú, bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
Drottinn, slíttu úr þeim eiturbroddinn!
6 Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run; ní ẹnu wọn, ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.
Dragðu vígtennurnar úr þessum vörgum, ó Guð.
7 Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ; nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
Láttu þá hverfa eins og jörðin hafi gleypt þá. Sláðu vopnin úr höndum þeirra.
8 Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
Láttu þá þorna upp eins og snigla og ekki sjá sólina frekar en þeir sem andvana eru fæddir.
9 Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún; bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
Guð mun svipta þeim burt, eyða þeim skjótar en pottur hitnar yfir eldi.
10 Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn, nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
Þá munu hinir guðhræddu fagna, þegar réttlætið sigrar og þeir fá að ganga um blóðidrifin stræti fallinna óvina.
11 Àwọn ènìyàn yóò wí pé, “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo; lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”
Þá munu menn sjá að réttlætið sigrar og að Guð dæmir jörðina með réttvísi.