< Psalms 58 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́ ẹ̀yin ìjọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
Mictam de David, [donné] au maître chantre, [pour le chanter] sur Al-tasheth. En vérité, vous gens de l'assemblée, prononcez-vous ce qui est juste? Vous fils des hommes, jugez-vous avec droiture.
2 Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo, ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
Au contraire, vous tramez des injustices dans votre cœur; vous balancez la violence de vos mains en la terre.
3 Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà, lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
Les méchants se sont égarés dès la matrice, ils ont erré dès le ventre [de leur mère], en parlant faussement.
4 Oró wọn dàbí oró ejò, wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
Ils ont un venin semblable au venin du serpent, [et] ils sont comme l'aspic sourd, qui bouche son oreille;
5 tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú, bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
Qui n'écoute point la voix des enchanteurs, [la voix] du charmeur fort expert en charmes.
6 Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run; ní ẹnu wọn, ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.
Ô Dieu, brise-leur les dents dans leur bouche! Eternel, romps les dents mâchelières des lionceaux.
7 Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ; nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
Qu'ils s'écoulent comme de l'eau, et qu'ils se fondent! que [chacun d'eux] bande [son arc, mais] que ses flèches soient comme si elles étaient rompues!
8 Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
Qu'il s'en aille comme un limaçon qui se fond! qu'ils ne voient point le soleil non plus que l'avorton d'une femme!
9 Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún; bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
Avant que vos chaudières aient senti le feu des épines, l'ardeur de la colère, semblable à un tourbillon, enlèvera [chacun d'eux] comme de la chair crue.
10 Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn, nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
Le juste se réjouira quand il aura vu la vengeance; il lavera ses pieds au sang du méchant.
11 Àwọn ènìyàn yóò wí pé, “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo; lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”
Et chacun dira: quoi qu'il en soit, il y a une récompense pour le juste; quoi qu'il en soit, il y a un Dieu qui juge en la terre.

< Psalms 58 >