< Psalms 58 >
1 Fún adarí orin. Tí ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòótọ́ ẹ̀yin ìjọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ẹ̀yin ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?
Pour le chef musicien. Sur l'air de « Do Not Destroy ». Un poème de David. Parlez-vous vraiment de la justice, vous qui êtes silencieux? Jugez-vous de manière irréprochable, fils d'hommes?
2 Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìṣòdodo, ọwọ́ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.
Non, dans ton cœur, tu complotes l'injustice. Tu mesures la violence de tes mains dans la terre.
3 Ní inú ìyá wọn wá ni ènìyàn búburú tí ṣìnà, lójúkan náà tí a ti bí wọn, wọn a máa ṣèké.
Les méchants s'égarent dès le sein maternel. Ils sont dévoyés dès leur naissance, ils disent des mensonges.
4 Oró wọn dàbí oró ejò, wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara rẹ̀ ni etí,
Leur poison est comme celui d'un serpent, comme un cobra sourd qui bouche son oreille,
5 tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atunilójú, bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.
qui n'écoute pas la voix des charmeurs, peu importe l'habileté du charmeur.
6 Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run; ní ẹnu wọn, ká ọ̀gàn àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.
Brise-leur les dents, Dieu, dans leur bouche. Sors les grandes dents des jeunes lions, Yahvé.
7 Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń sàn lọ; nígbà tí ó bá fa ọfà rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.
Qu'ils disparaissent comme l'eau qui s'écoule. Quand ils tirent l'arc, que leurs flèches soient émoussées.
8 Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbé bí ọmọ tí oṣù rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí oòrùn.
Qu'ils soient comme un escargot qui fond et passe, comme l'enfant mort-né, qui n'a pas vu le soleil.
9 Kí ìkòkò yín kí ó tó mọ ìgbóná ẹ̀gún; bóyá ní tútù tàbí ní gbígbẹ, yóò fi ìjì gbá wọn lọ.
Avant que vos pots puissent sentir la chaleur des épines, il balaiera les verts et les brûlants.
10 Olódodo yóò yọ̀ nígbà a bá ń gbẹ̀san wọn, nígbà tí wọn bá wẹ ẹsẹ̀ wọn nínú ẹ̀jẹ̀ ènìyàn búburú.
Le juste se réjouira quand il verra la vengeance. Il lavera ses pieds dans le sang des méchants,
11 Àwọn ènìyàn yóò wí pé, “Lóòtítọ́ èrè àwọn ń bẹ fún olódodo; lóòtítọ́ òun ni Ọlọ́run tí ń ṣe ìdájọ́ ní ayé.”
de sorte que les hommes diront: « Il y a certainement une récompense pour les justes. Il y a certainement un Dieu qui juge la terre. »