< Psalms 57 >
1 Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi, nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà. Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
Przedniejszemu śpiewakowi, jako: Nie zatracaj, złoty psalm Dawidowy, kiedy uciekał przed Saulem do jaskini. Zmiłuj się nademną, o Boże! zmiłuj się nademną; albowiem w tobie ufa dusza moja, a do cienia skrzydeł twoich uciekam się; aż przeminie utrapienie.
2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
Będę wołał do Boga najwyższego, do Boga, który wykonywa sprawę moję.
3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá, yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi. Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
On pośle z nieba, i wybawi mię od pohańbienia tego, który mię chce pochłonąć. (Sela) Pośle mi Bóg miłosierdzie swoje i prawdę swą.
4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún; mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú, àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
Dusza moja jest w pośród lwów; leżę miedzy palącymi, między synami ludzkimi, których zęby jako włócznie i strzały, i język ich miecz ostry.
5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
Wywyżże się nad niebiosa, o Boże! a nade wszystką ziemią chwała twoja.
6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi: a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú, wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi: ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
Sieci zastawili na nogi moje, nachylili duszę moję, wykopali dół przed obliczem mojem; ale sami wpadli weń. (Sela)
7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run; ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
Gotowe jest serce moje, Boże! gotowe jest serce moje; śpiewać i wychwalać cię będę.
8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Jí, ohun orin èlò àti dùùrù! Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
Ocuć się chwało moja! ocuć się, lutnio i harfo! gdy na świtaniu powstaję.
9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
Będę cię wysławiał między ludem, Panie! a będęć śpiewał między narodami.
10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run; òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
Albowiem wielkie jest aż do niebios miłosierdzie twoje, i aż pod obłoki prawda twoja.
11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ; kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
Wywyżże się nad niebiosa, o Boże! a nade wszystką ziemię wywyż chwałę twoję.