< Psalms 57 >

1 Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi, nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà. Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
Ne perdez pas entièrement; par David, pour une inscription de titre, lorsqu’il s’enfuit de devant la face de Saül dans la caverne. Ayez pitié de moi, ô Dieu, ayez pitié de moi, parce que mon âme s’est confiée en vous. Et à l’ombre de vos ailes, j’espérerai jusqu’à ce que l’iniquité soit passée.
2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
Je crierai au Dieu très haut, au Dieu qui m’a fait du bien.
3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá, yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi. Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
Il a envoyé du ciel, et il m’a délivré: il a donné en opprobre ceux qui me foulaient aux pieds. Dieu a envoyé sa miséricorde et sa vérité,
4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún; mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú, àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
Et il a arraché mon âme du milieu des petits des lions: j’ai dormi tout troublé. Les fils des hommes, leurs dents sont des armes et des flèches, et leur langue un glaive acéré.
5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
Élevez-vous au-dessus des cieux, ô Dieu, et que sur toute la terre éclate votre gloire.
6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi: a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú, wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi: ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
Ils ont préparé un lacs pour mes pieds, et ils ont courbé mon âme. Ils ont creusé devant ma face une fosse, et ils y sont tombés.
7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run; ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
Mon cœur est prêt, ô Dieu, mon cœur est prêt: je chanterai et je dirai un psaume.
8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Jí, ohun orin èlò àti dùùrù! Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
Lève-toi, ô ma gloire, lève-toi, psaltérion, et toi, harpe: je me lèverai au point du jour.
9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
Je vous louerai parmi les peuples. Seigneur, et je dirai un psaume en votre honneur parmi les nations.
10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run; òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
Parce que votre miséricorde s’est élevée jusqu’aux cieux, et votre vérité jusqu’aux nues.
11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ; kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
Soyez exalté au-dessus des cieux, ô Dieu, et que sur toute la terre éclate votre gloire.

< Psalms 57 >