< Psalms 57 >
1 Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi, nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà. Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
Au maître-chantre. — «Ne détruis pas.» — Poème de David, lorsqu'il s'enfuit dans la caverne, poursuivi par Saül. Aie pitié, ô Dieu, aie pitié de moi; Car mon âme cherche en toi son refuge. Je me réfugie à l'ombre de tes ailes. Jusqu'à ce que la calamité soit passée.
2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
Je crie vers le Dieu Très-Haut, Vers le Dieu fort qui agira pour moi.
3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá, yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi. Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
Il m'enverra des cieux sa délivrance. Tandis que mon persécuteur me couvre d'outrages. (Pause) Oui, Dieu m'enverra sa grâce et son secours fidèle.
4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún; mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú, àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
Mon âme est au milieu des lions; J'habite avec des hommes qui vomissent des flammes Dont les dents sont des lances et des flèches, Et dont la langue est un glaive acéré.
5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
Dieu, élève-toi au-dessus des cieux! Que ta gloire couvre toute la terre!
6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi: a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú, wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi: ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
Ils avaient tendu un piège sous mes pas; Mon âme chancelait; Ils avaient creusé une fosse devant moi: Ils y sont tombés! (Pause)
7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run; ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
Mon coeur est bien disposé, ô Dieu! Oui, mon coeur est bien disposé Pour chanter, pour psalmodier.
8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Jí, ohun orin èlò àti dùùrù! Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
Réveille-toi, mon âme; réveillez-vous, mon luth et ma harpe: Je veux devancer l'aurore.
9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
Je te célébrerai parmi les peuples. Seigneur! Je te louerai parmi les nations;
10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run; òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
Car ta bonté atteint jusqu'aux cieux. Et ta fidélité jusqu'aux nues.
11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ; kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
O Dieu, élève-toi au-dessus des cieux! Que ta gloire couvre toute la terre!