< Psalms 57 >

1 Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi, nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà. Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
For the Chief Musician; [set to] Al-tashheth. [A Psalm] of David: Michtam: when he fled from Saul, in the cave. Be merciful unto me, O God, be merciful unto me; for my soul taketh refuge in thee: yea, in the shadow of thy wings will I take refuge, until [these] calamities be overpast.
2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
I will cry unto God Most High; unto God that performeth [all things] for me.
3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá, yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi. Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
He shall send from heaven, and save me, [when] he that would swallow me up reproacheth; (Selah) God shall send forth his mercy and his truth.
4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún; mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú, àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
My soul is among lions; I lie among them that are set on fire, even the sons of men, whose teeth are spears and arrows, and their tongue a sharp sword.
5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
Be thou exalted, O God, above the heavens; [let] thy glory [be] above all the earth.
6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi: a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú, wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi: ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
They have prepared a net for my steps; thy soul is bowed down: they have digged a pit before me; they are fallen into the midst thereof themselves. (Selah)
7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run; ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
My heart is fixed, O God, my heart is fixed: I will sing, yea, I will sing praises.
8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Jí, ohun orin èlò àti dùùrù! Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
Awake up, my glory; awake, psaltery and harp: I myself will awake right early.
9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
I will give thanks unto thee, O Lord, among the peoples: I will sing praises unto thee among the nations.
10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run; òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
For thy mercy is great unto the heavens, and thy truth unto the skies.
11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ; kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
Be thou exalted, O God, above the heavens; [let] thy glory [be] above all the earth.

< Psalms 57 >