< Psalms 57 >

1 Fún adarí orin. Ní ohùn “Má ṣe parun.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi, nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà. Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.
To him that excelleth. Destroy not. A Psalme of David on Michtam. When he fled from Saul in the cave. Have mercie vpon me, O God, haue mercie vpon me: for my soule trusteth in thee, and in the shadowe of thy wings wil I trust, till these afflictions ouerpasse.
2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ, sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.
I will call vnto the most high God, euen to the God, that performeth his promise toward me.
3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá, yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi. Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.
He will send from heauen, and saue me from the reproofe of him that would swallowe me. (Selah) God wil send his mercy, and his trueth.
4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún; mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú, àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.
My soule is among lions: I lie among the children of men, that are set on fire: whose teeth are speares and arrowes, and their tongue a sharpe sworde.
5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ, kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.
Exalt thy selfe, O God, aboue the heauen, and let thy glory be vpon all the earth.
6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi: a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú, wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi: ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.
They haue layd a net for my steps: my soule is pressed downe: they haue digged a pit before me, and are fallen into the mids of it. (Selah)
7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run; ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.
Mine heart is prepared, O God, mine heart is prepared: I will sing and giue prayse.
8 Jí, ìwọ ọkàn mi! Jí, ohun orin èlò àti dùùrù! Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.
Awake my tongue, awake viole and harpe: I wil awake early.
9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.
I will prayse thee, O Lord, among the people, and I wil sing vnto thee among the nations.
10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run; òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.
For thy mercie is great vnto the heauens, and thy trueth vnto the cloudes.
11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ; kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.
Exalt thy selfe, O God, aboue the heauens, and let thy glory be vpon all the earth.

< Psalms 57 >