< Psalms 56 >

1 Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi; ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára.
Načelniku godbe, o duši, ki silo trpi od tujcev krdela, odlična pesem Davidova, ko so ga prijeli Filistejci v Gatu. Milosten mi bodi, Bog, ker rohneč me preganja človek, ves dan me stiska oblegovatelj.
2 Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́, àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.
Rohné zalezovalci moji vés dan, ker mnogo jih je; z višave naj mi pomagajo borilci.
3 Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí, èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Ko se bodem bal, zaupal bodem v tebe.
4 Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ, nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?
V Bogu bodem hvalil besedo njegovo; v Boga bodem zaupal, ne bodem se bal: Kaj naj bi mi storilo meso?
5 Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́, wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.
Ves dan žalijo mojo stvar; zoper mene merijo vse njih misli v hudo.
6 Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba. Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.
Zbirajo, skrivajo se oni; na moj sled prežé, kakor ki iščejo življenje moje.
7 San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn; ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.
Poleg krivičnosti jim stóri, v jezi pahni ljudstva, Bog.
8 Kọ ẹkún mi sílẹ̀; kó omijé mi sí ìgò rẹ, wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?
Ti imaš sešteto tavanje moje; v meh svoj deni vsako solzo mojo, ali bi jih ne imel seštetih?
9 Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́ nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.
Tedaj se povrnejo sovražniki moji nazaj; tisti dan, ko bodem vpil: To vém, da mi bode Bog na strani.
10 Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,
V Bogu bodem hvalil besedo, v Gospodu hvalil besedo.
11 nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi: ẹ̀rù kì yóò bà mí. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
V Boga zaupam, ne bodem se bal; kaj bi mi storil človek?
12 Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run: èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.
Z menoj bodejo, o Bog, obljube tvoje; zahvaljeval se bodem tebi.
13 Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú, kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.
Ker dušo mojo otimaš smrti; ali bi ne rešil nóg mojih padca? da neprestano hodim pred Bogom v tega življenja luči.

< Psalms 56 >