< Psalms 56 >

1 Fún adarí orin. Ti ohùn “Àdàbà lórí Óákù òkè réré.” Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí àwọn ará Filistini ka mọ́ ní Gati. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, nítorí àwọn ènìyàn ń fi ìgbónára lépa mi; ní gbogbo ọjọ́ ni wọn ń kọjú ìjà sí mi, wọn ń ni mi lára.
Au maître de chant. Sur la Colombe muette des pays lointains. Hymne de David. Lorsque les Philistins le saisirent à Geth. Aie pitié de moi, ô Dieu, car l’homme s’acharne après moi; tout le jour on me fait la guerre, on me persécute.
2 Àwọn ọ̀tá mi ń lé mi ní gbogbo ọjọ́, àwọn ènìyàn ń kọjú ìjà sí mi nínú ìgbéraga wọn.
Tout le jour mes adversaires me harcèlent; car ils sont nombreux ceux qui me combattent le front levé.
3 Nígbà tí ẹ̀rù bà ń bà mí, èmi o gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Quand je suis dans la crainte, je me confie en toi.
4 Nínú Ọlọ́run èmi yóò máa yìn ọ̀rọ̀ rẹ, nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi; ẹ̀rù kì yóò bà mí kí ni ẹran-ara lè ṣe sí mi?
Par le secours de Dieu, je célébrerai l’accomplissement de sa parole. Je me confie en Dieu, je ne crains rien: que peut me faire un faible mortel?
5 Wọn ń yí ọ̀rọ̀ mí ní gbogbo ọjọ́, wọn ń gbèrò nígbà gbogbo láti ṣe mí níbi.
Sans cesse ils enveniment mes paroles, toutes leurs pensées sont contre moi pour me perdre.
6 Wọn kó ara wọn jọ, wọ́n ba. Wọ́n ń ṣọ́ ìgbésẹ̀ mi wọn ń làkàkà láti gba ẹ̀mí mi.
Ils complotent, ils apostent des espions, ils observent mes traces, parce qu’ils en veulent à ma vie.
7 San ẹ̀san iṣẹ́ búburú wọ́n fún wọn; ní ìbínú rẹ, Ọlọ́run, wọ́ àwọn ènìyàn náà bọ́ sílẹ̀.
Chargés de tant de crimes, échapperont-ils? Dans ta colère, ô Dieu, abats les peuples!
8 Kọ ẹkún mi sílẹ̀; kó omijé mi sí ìgò rẹ, wọ́n kò ha sí nínú ìkọ̀sílẹ̀ rẹ bí?
Tu as compté les pas de ma vie errante, tu as recueilli mes larmes dans ton outre: ne sont-elles pas inscrites dans ton livre?
9 Nígbà náà ni àwọn ọ̀tá mi yóò pẹ̀yìndà nígbà tí mo bá pè fún ìrànlọ́wọ́ nípa èyí ni mo mọ̀ pé Ọlọ́run ń bẹ fún mi.
Alors mes ennemis retourneront en arrière, au jour où je t’invoquerai; je le sais, Dieu est pour moi.
10 Nínú Ọlọ́run, ẹni tí mo yìn ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú Olúwa, ẹni tí mo yin ọ̀rọ̀ rẹ̀,
Par le secours de Dieu, je célébrerai l’accomplissement de sa parole; par le secours de Yahweh, je célébrerai l’accomplissement de sa promesse.
11 nínú Ọlọ́run ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi: ẹ̀rù kì yóò bà mí. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Je me confie en Dieu, je ne crains rien: Que peut me faire un faible mortel?
12 Mo jẹ́ ẹ̀jẹ́ lábẹ́ rẹ Ọlọ́run: èmi o mú ìyìn mi wá fún ọ.
Les vœux que je t’ai faits, ô Dieu, j’ai à les acquitter; je t’offrirai des sacrifices d’actions de grâces.
13 Nítorí ìwọ tí gbà mí lọ́wọ́ ikú àti ẹsẹ̀ mi lọ́wọ́ ìṣubú, kí èmí lè máa rìn níwájú Ọlọ́run ní ìmọ́lẹ̀ àwọn alààyè.
Car tu as délivré mon âme de la mort, — n’as-tu pas préservé mes pieds de la chute? — afin que je marche devant Dieu à la lumière des vivants.

< Psalms 56 >