< Psalms 55 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run, má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:
Przewodnikowi chóru, na Neginot. Pieśń pouczająca Dawida. Boże, nakłoń ucha ku mojej modlitwie i nie ukrywaj się przed moją prośbą.
2 gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn. Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.
Posłuchaj uważnie i wysłuchaj mnie; uskarżam się w swej modlitwie i jęczę;
3 Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni, nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú; nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi, wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.
Z powodu głosu wroga, z powodu ucisku niegodziwego; zwalają na mnie nieprawość i w gniewie sprzeciwiają mi się.
4 Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú; ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.
Moje serce boleje we mnie i dopadł mnie strach przed śmiercią.
5 Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi; ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.
Przyszły na mnie bojaźń i drżenie i przejęła mnie trwoga.
6 Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà! Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.
I powiedziałem: O, gdybym miał skrzydła jak gołębica, uleciałbym i odpoczął.
7 Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré, kí ń sì dúró sí aginjù;
Oto bym uleciał daleko i zamieszkał na pustyni. (Sela)
8 èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò, jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”
Pospieszyłbym, aby ujść [przed] wichrem i nawałnicą.
9 Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú, nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.
Zniszcz, Panie, rozdziel ich język, bo widzę przemoc i niezgodę w mieście.
10 Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri; ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.
Dniem i nocą krążą wokoło po jego murach, a wewnątrz niego zło i ucisk.
11 Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀; ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.
Wewnątrz niego [jest] niegodziwość, a z jego ulic nie znika oszustwo i podstęp.
12 Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi, èmi yóò fi ara mọ́ ọn; tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi, èmi ìbá sá pamọ́ fún un.
Bo [to] nie wróg mnie lżył, co mógłbym znieść; nie powstał przeciwko mnie ten, który mnie nienawidził – [wtedy] ukryłbym się przed nim;
13 Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi, ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,
Ale ty, człowiek równy mi, mój wódz i przyjaciel.
14 pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀, bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.
Mile naradzaliśmy się ze sobą i razem chodziliśmy do domu Bożego.
15 Kí ikú kí ó dé bá wọn, kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú, jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà, nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn. (Sheol h7585)
Niech śmierć ich zaskoczy, niech żywcem zstąpią do piekła, bo w ich domach i wśród nich [mieszka] zło. (Sheol h7585)
16 Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run; Olúwa yóò sì gbà mí.
Ja zaś do Boga zawołam i PAN mnie wybawi.
17 Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú, o sì gbọ́ ohùn mi.
Wieczorem, rano i w południe będę się modlić i głośno wołać, a on wysłucha mego głosu.
18 Ó rà mí padà láìléwu kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.
Odkupił moją duszę, abym miał spokój od walki, jaką ze mną toczyli, bo wielu ich było przy mnie.
19 Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì (Sela) nítorí tí wọn kò ní àyípadà, tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.
Bóg wysłucha i będzie ich trapić ten, który trwa od wieków. (Sela) [Bo] nie poprawiają się i nie boją się Boga.
20 Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀; ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.
Podniósł rękę na tych, którzy utrzymywali z nim pokój; złamał swoje przymierze.
21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́, ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀; ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ, ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.
Gładsze niż masło były [słowa] jego ust, lecz wrogość [miał] w sercu; miększe niż oliwa jego słowa, ale były jak obnażone miecze.
22 Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa yóò sì mú ọ dúró; òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.
Przerzuć swój ciężar na PANA, a on cię podtrzyma; nie dopuści nigdy, by miał się zachwiać sprawiedliwy.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi wá sí ihò ìparun; àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn, kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn. Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Ale ty, Boże, wtrącisz ich w dół zatracenia; ludzie krwawi i podstępni nie dożyją połowy swoich dni; ja zaś zaufam tobie.

< Psalms 55 >