< Psalms 55 >
1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run, má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:
Az éneklőmesternek, hangszerekkel; Dávid tanítása. Hallgasd meg, Isten, az én imádságomat, és ne rejtsd el magadat az én könyörgésem elől;
2 gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn. Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.
Figyelmezz én reám és hallgass meg engemet; mert keseregve bolyongok és jajgatok!
3 Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni, nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú; nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi, wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.
Az ellenségnek szaváért és a hitetlenek nyomorgatásáért: mert hazugságot hárítanak reám, és nagy dühösséggel ellenkeznek velem.
4 Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú; ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.
Az én szívem reszket bennem, és a halál félelmei körülvettek engem.
5 Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi; ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.
Félelem és rettegés esett én reám, és borzadály vett körül engem.
6 Èmi sọ pé, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà! Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.
Mondám: Vajha szárnyam volna, mint a galambnak! Elrepülnék és nyugodnám.
7 Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré, kí ń sì dúró sí aginjù;
Ímé, messze elmennék és a pusztában lakoznám. (Szela)
8 èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò, jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle.”
Sietnék kiszabadulni e sebes szélből, e forgószélből.
9 Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú, nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.
Rontsd meg Uram, és oszlasd meg az ő nyelvöket; mert erőszakot és háborgást látok a városban.
10 Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri; ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.
Nappal és éjjel körüljárják azt annak kőfalainál, bent hamisság és ártalom van abban.
11 Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀; ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.
Veszedelem van bensejében; s nem távozik annak teréről a zsarnokság és csalárdság.
12 Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi, èmi yóò fi ara mọ́ ọn; tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi, èmi ìbá sá pamọ́ fún un.
Mert nem ellenség szidalmazott engem, hisz azt elszenvedném; nem gyűlölőm emelte fel magát ellenem, hiszen elrejtettem volna magamat az elől:
13 Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi, ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,
Hanem te, hozzám hasonló halandó, én barátom és ismerősöm,
14 pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀, bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.
A kik együtt édes bizalomban éltünk; az Isten házába jártunk a tömegben.
15 Kí ikú kí ó dé bá wọn, kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú, jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà, nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn. (Sheol )
A halál vegye őket körül, elevenen szálljanak a Seolba; mert gonoszság van lakásukban, kebelökben. (Sheol )
16 Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run; Olúwa yóò sì gbà mí.
Én az Istenhez kiáltok, és az Úr megszabadít engem.
17 Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú, o sì gbọ́ ohùn mi.
Estve, reggel és délben panaszkodom és sóhajtozom, és ő meghallja az én szómat.
18 Ó rà mí padà láìléwu kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.
Megszabadítja lelkemet békességre a rám támadó hadtól, mert sokan vannak ellenem.
19 Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì (Sela) nítorí tí wọn kò ní àyípadà, tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.
Meghallja Isten és megfelel nékik, (mivelhogy ő eleitől fogva trónol, (Szela) a kik nem akarnak megváltozni és nem félik az Istent.
20 Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀; ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.
Kezeit felemelte a vele békességben lévőkre; megszegte az ő szövetségét.
21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́, ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀; ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ, ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.
A vajnál simább az ő szája, pedig szívében háborúság van; lágyabbak beszédei az olajnál, pedig éles szablyák azok.
22 Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa yóò sì mú ọ dúró; òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.
Vessed az Úrra a te terhedet, ő gondot visel rólad, és nem engedi, hogy valamikor ingadozzék az igaz.
23 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi wá sí ihò ìparun; àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn, kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn. Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.
Te, Isten, a veszedelem vermébe taszítod őket; a vérszopó és álnok emberek életüknek felét sem élik meg; én pedig te benned bízom.