< Psalms 54 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
Przedniejszemu śpiewakowi na Neginot pieśń Dawidowa nauczająca. Gdy przyszli Zyfejczycy, i rzekli do Saula: Dawid się kryje przed tobą u nas. Boże! dla imienia twego wybaw mię, a w mocy twojej podejmij się sprawy mojej.
2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Boże! wysłuchaj modlitwę moję; przyjmij w uszy słowa ust moich.
3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
Albowiem obcy powstali przeciwko mnie, a okrutnicy szukają duszy mojej, nie stawiając sobie Boga przed oczyma swemi. (Sela)
4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Oto Bóg jest pomocnikiem moim: Pan jest z tymi, którzy podpierają żywot mój.
5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Oddaj złym nieprzyjaciołom moim, w prawdzie twojej wytrać ich, o Panie!
6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
Tedyć dobrowolnie będę ofiarował; będę wysławiał imię twoje, Panie! przeto, że jest dobre;
7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.
Gdyż z każdego utrapienia wyrwałeś mię, a pomstę nad nieprzyjaciołmi mymi oglądało oko moje.

< Psalms 54 >