< Psalms 54 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
Maskil de David, [donné] au maître chantre, [pour le chanter] sur Néguinoth. Touchant ce que les Ziphiens vinrent à Saül, et lui dirent: David ne se tient-il pas caché parmi nous? Ô Dieu, délivre-moi par ton Nom, et me fais justice par ta puissance.
2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
Ô Dieu, écoute ma requête, [et] prête l'oreille aux paroles de ma bouche.
3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
Car des étrangers se sont élevés contre moi, et des gens terribles, qui n'ont point Dieu devant leurs yeux, cherchent ma vie; (Sélah)
4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Voilà, Dieu m'accorde son secours; le Seigneur [est] de ceux qui soutiennent mon âme.
5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Il fera retourner le mal sur ceux qui m'épient; détruis-les selon ta vérité.
6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
Je te ferai sacrifice de bon cœur; Eternel! je célébrerai ton Nom, parce qu'il est bon.
7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.
Car il m'a délivré de toute détresse: et mon œil a vu [ce qu'il voulait voir] en mes ennemis.

< Psalms 54 >