< Psalms 54 >

1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
To the Chief Musician: with Stringed Instruments. A Psalm of Instruction, of David. When the Ziphites came and said unto Saul, Is not, David, hiding himself, with us? O God! by thine own Name, save me, And, by thine own strength, wilt thou vindicate me?
2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
O God! Hear my prayer, Give ear to the sayings of my mouth;
3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
For, aliens, have risen up against me, And, men of violence, have sought my life, They have not set God before them. (Selah)
4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Lo! God, is bringing me help, My Lord, is with the upholders of my life;
5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
Let him turn back the mischief upon mine adversaries, In thy faithfulness, destroy them!
6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
With a freewill-offering, will I sacrifice unto thee, I will praise thy Name, O Yahweh, for it is good;
7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.
For, out of all distress, hath he rescued me, —And, upon my foes, hath, mine own eye, looked.

< Psalms 54 >