< Psalms 54 >
1 Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
For the end, amongst Hymns of instruction by David, when the Ziphites came and said to Saul, Behold, is not David hid with us? Save me, O God, by your name, and judge me by your might.
2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
O God, hear my prayer; listen to the words of my mouth.
3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
For strangers have risen up against me, and mighty men have sought my life: they have not set God before them. (Pause)
4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
For behold! God assists me; and the Lord is the helper of my soul.
5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
He shall return evil to mine enemies; utterly destroy them in your truth.
6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
I will willingly sacrifice to you: I will give thanks to your name, O Lord; for [it is] good.
7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.
For you have delivered me out of all affliction, and mine eye has seen [my desire] upon mine enemies.