< Psalms 53 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí mahalati. Maskili ti Dafidi. Aṣiwèrè wí ní ọkàn rẹ̀ pé, “Ọlọ́run kò sí.” Wọ́n bàjẹ́, gbogbo ọ̀nà wọn sì burú; kò sì ṣí ẹnìkan tí ń ṣe rere.
Przedniejszemu śpiewakowi na Machalat pieśń Dawidowa nauczająca. Głupi rzekł w sercu swem: Niemasz Boga. Popsowali się, i obrzydliwą czynią nieprawość; niemasz, ktoby czynił dobrze.
2 Ọlọ́run bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run sórí àwọn ọmọ ènìyàn, láti wò bóyá ẹnìkan wà, tí ó ní òye, tí ó sì ń wá Ọlọ́run.
Bóg z niebios spojrzał na synów ludzkich, aby obaczył, byłliby kto rozumny i szukający Boga.
3 Gbogbo ènìyàn tí ó ti yí padà, wọ́n ti parapọ̀ di ìbàjẹ́; kò sí ẹnìkan tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
Aleć oni wszyscy odstąpili, jednako się nieużytecznymi stali: niemasz, ktoby czynił dobrze, niemasz, i jednego.
4 Ṣé àwọn oníṣẹ́ búburú kò ní ìmọ̀? Àwọn ẹni tí ń jẹ ènìyàn mi, bí ẹni jẹun tí wọn kò sì pe Ọlọ́run?
Azaż nie wiedzą wszyscy czyniciele nieprawości, że pożerają lud mój, jako więc chleb jedzą? ale Boga nie wzywają.
5 Níbẹ̀ ni ìwọ gbé wà ní ìbẹ̀rù ńlá níbi tí ẹ̀rù kò gbé sí, nítorí Ọlọ́run tí fọ́n egungun àwọn tí ó dó tì ọ́ ká; ìwọ tí dójútì wọ́n, nítorí Ọlọ́run ti kẹ́gàn wọn.
Tam się bardzo ulękną, gdzie niemasz strachu; albowiem Bóg rozproszy kości tych, którzy cię oblegli; ty ich pohańbisz, bo ich Bóg wzgardzi.
6 Ìgbàlà Israẹli ìbá jáde wá láti Sioni! Nígbà tí Ọlọ́run bá mú ohun ìní àwọn ènìyàn rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jakọbu yọ̀ kí inú Israẹli sì máa dùn!
Któż da z Syonu wybawienie Izraelowi? Gdy Bóg przywróci z więzienia lud swój, rozraduje się Jakób, rozweseli się Izrael.

< Psalms 53 >