< Psalms 53 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí mahalati. Maskili ti Dafidi. Aṣiwèrè wí ní ọkàn rẹ̀ pé, “Ọlọ́run kò sí.” Wọ́n bàjẹ́, gbogbo ọ̀nà wọn sì burú; kò sì ṣí ẹnìkan tí ń ṣe rere.
Au chef des chantres; sur Mahalat. Maskîl de David. L’Impie a dit en son cœur: "Il n’est point de Dieu!" On est corrompu, on commet des actes odieux; personne ne fait le bien.
2 Ọlọ́run bojú wo ilẹ̀ láti ọ̀run sórí àwọn ọmọ ènìyàn, láti wò bóyá ẹnìkan wà, tí ó ní òye, tí ó sì ń wá Ọlọ́run.
Dieu, du haut du ciel, regarde les hommes, pour voir s’il en est de bien inspirés, recherchant Dieu.
3 Gbogbo ènìyàn tí ó ti yí padà, wọ́n ti parapọ̀ di ìbàjẹ́; kò sí ẹnìkan tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
Tous ils ont dévié, ensemble ils sont pervertis; personne n’agit bien, pas même un seul.
4 Ṣé àwọn oníṣẹ́ búburú kò ní ìmọ̀? Àwọn ẹni tí ń jẹ ènìyàn mi, bí ẹni jẹun tí wọn kò sì pe Ọlọ́run?
Ah! ils s’en ressentiront, tous ces ouvriers d’iniquité, qui dévorent mon peuple comme on mange du pain, et n’invoquent point Dieu.
5 Níbẹ̀ ni ìwọ gbé wà ní ìbẹ̀rù ńlá níbi tí ẹ̀rù kò gbé sí, nítorí Ọlọ́run tí fọ́n egungun àwọn tí ó dó tì ọ́ ká; ìwọ tí dójútì wọ́n, nítorí Ọlọ́run ti kẹ́gàn wọn.
Là même ils seront saisis d’effroi, où il n’y a pas lieu de s’effrayer; car Dieu disperse les membres de ceux qui t’assiègent. Tu les couvres de honte, Dieu les ayant rejetés.
6 Ìgbàlà Israẹli ìbá jáde wá láti Sioni! Nígbà tí Ọlọ́run bá mú ohun ìní àwọn ènìyàn rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jakọbu yọ̀ kí inú Israẹli sì máa dùn!
Ah! puisse venir de Sion le salut d’Israël! Quand Dieu ramènera les captifs de son peuple, Jacob jubilera, Israël sera dans la joie.

< Psalms 53 >