< Psalms 52 >
1 Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
Jusqu'à la Fin; instruction de David, Quand Doeg l'Iduméen alla porter un message à Saül, et lui dit: David est entré dans la maison d'Abimélech, Qu'as-tu à t'enorgueillir dans ta malice, homme puissant en iniquité?
2 Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
Ta langue tous les jours a tramé l'injustice; tu t'es servi de la fraude comme d'un rasoir tranchant.
3 Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
Tu as préféré la malice à la bonté; tu as dit: L'iniquité plutôt que la justice.
4 Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
Tu as préféré les paroles de ruine, à langue trompeuse!
5 Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
A cause de cela, Dieu à la fin te détruira; il t'arrachera et te chassera de ta demeure, et extirpera ta racine de la terre des vivants.
6 Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
Et les justes le verront, et ils en seront effrayés et ils riront de toi, et diront:
7 “Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
Voilà un homme qui n'avait point pris Dieu pour champion, mais qui avait mis son espoir en l'abondance de ses richesses, et qui s'était cru fort en sa vanité.
8 Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
Pour moi, comme un olivier fertile en la maison de Dieu, j'ai espéré en la miséricorde de Dieu, à jamais et dans tous les siècles des siècles.
9 Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.
Je te rendrai grâces éternellement, à cause de tes œuvres, et j'attendrai ton nom, parce qu'il est bon pour tes saints.