< Psalms 52 >

1 Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
Přednímu z kantorů, vyučující žalm Davidův. Když přišel Doeg Idumejský, a zvěstoval Saulovi, a pověděl mu, že David všel do domu Achimelechova. Proč se chlubíš nešlechetností, ty mocný? Milosrdenstvíť Boha silného trvá každého dne.
2 Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
Těžkosti obmýšlí jazyk tvůj, tak jako břitva nabroušená lest provodí.
3 Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
Miluješ zlé více než dobré, raději lež mluvíš než spravedlnost. (Sélah)
4 Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
Miluješ všelijaké řeči k sehlcení, a jazyk ošemetný.
5 Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
I tebeť Bůh silný zkazí na věky, pochytí tě, a vytrhne tě z stánku, a vykoření z země živých. (Sélah)
6 Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
Což spravedliví vidouce, budou se báti a jemu posmívati:
7 “Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
Aj, toť jest ten člověk, kterýž neskládal v Bohu síly své, ale doufaje ve množství bohatství svých, zmocňoval se v zlosti své.
8 Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
Já pak budu jako oliva zelenající se v domě Božím; neboť jsem naději složil v milosrdenství Božím na věky věků.
9 Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.
Oslavovati tě budu, Pane, na věky, že jsi to učinil, a poshovím na jméno tvé, neboť jest vzácné před oblíčejem svatých tvých.

< Psalms 52 >