< Psalms 51 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀ kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
Ki te tino kaiwhakatangi. He himene na Rawiri, i te taenga o Natana poropiti ki a ia, mo tona haerenga ki a Patehepa. Tohungia ahau, e te Atua, kia rite ki tou atawhai: kia rite ki tou aroha nui te murunga o oku he.
2 Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!
Horoia rawatia toku kino: kia ma hoki toku hara.
3 Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi, nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
E whaki ana hoki ahau i aku mahi tutu: kei toku aroaro tonu toku hara.
4 Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀, kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀, kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
He hara ki a koe, ki a koe anake, toku; i meatia ano tenei he ki tou aroaro; kia tika ai koe i tau korerotanga, kia ma ai hoki ina whakawa.
5 Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
Na i whakaahuatia ahau i roto i te kino, i runga ano i te hara toku whakahaputanga ki roto ki toku whaea.
6 Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú; ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.
Na ko tau e matenui ai ko te pono i nga wahi o roto, a ka whakaakona oku wahi ngaro e koe ki te whakaaro nui.
7 Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́; fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
Purea ahau ki te hihopa, a ka ma ahau; horoia ahau, a ka ma ke atu i te hukarere.
8 Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn; jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
Meinga kia rongo ahau i te hari, i te koa, a ka whakamanamana nga iwi i whatiia nei e koe.
9 Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.
Huna tou mata ki oku hara; a murua katoatia oku kino.
10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run, kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
Hanga, e te Atua, he ngakau ma ki roto ki ahau: whakahoutia hoki ki roto ki ahau he wairua tika.
11 Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ, kí o má ṣe gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
Kaua ahau e maka i tou aroaro; kaua hoki tou wairua tapu e tangohia i ahau.
12 Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá, kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.
Whakahokia mai ki ahau te hari o tau whakaoranga: tautokona hoki ahau ki te wairua kakama.
13 Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ, àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
Ko reira ahau whakaako ai i au ara ki te hunga tutu; a ka tahuri te hunga hara ki a koe.
14 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi, ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
Whakaorangia ahau i te hara toto, e te Atua, e te Atua o toku whakaoranga, a ka waiatatia au mahi tika e toku arero.
15 Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo, àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
Whakatuwheratia oku ngutu, e te Ariki; a ka puaki i toku mangai te whakamoemiti ki a koe.
16 Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá; Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
Kahore nei hoki koe e aro ki te patunga tapu; penei kua hoatu e ahau: kahore koe e ahuareka ki te tahunga tinana.
17 Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.
Ko nga patunga tapu ma te Atua he wairua maru: e kore koe e whakahawea e te Atua, ki te ngakau maru, ki te ngakau iro.
18 Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni, ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
Kia pai koe ki te atawhai i Hiona: hanga nga taiepa o Hiruharama.
19 Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo, pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun, nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.
Ko reira koe pai ai ki nga patunga tapu o te tika, ki nga tahunga tinana, he mea whakaeke katoa: ko reira ratou whakaeke ai i nga puru ki runga ki tou aata.