< Psalms 51 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀ kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
E ALOHA mai oe ia'u, e ke Akua, e like me kou lokomaikai; Mamuli o ka nui loa o kou aloha e hoopau i ko'u mau hala.
2 Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!
E holoi lea mai ia'u i pau kuu hewa; A e hoomaemae mai hoi ia'u i ko'u lawehala ana.
3 Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi, nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
No ka mea, ke hoike aku nei au i ko'u mau hala; Mau no hoi ko'u hewa imua o kuu alo.
4 Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀, kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀, kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
O oe, oe wale no ka'u i lawehala ai, A i hana hewa hoi imua o kou mau maka: I pono oe i kau olelo ana, I hemolele hoi i kuu hoahewa ana mai.
5 Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
Eia hoi, ua hanaia au maloko o ka hewa; Maloko o ka lawehala ana i hapai ai ko'u makuwahine ia'u.
6 Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú; ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.
Eia hoi, makemake oe i oiaio ko loko; A maloko o na wahi nalo e hoikeike mai oe ia'u i ka naauao.
7 Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́; fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
E huikala mai oe ia'u me ka husopa, a e maemae no wau: E holoi mai ia'u, a e oi aku kuu keokeo i ko ka hau.
8 Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn; jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
E haawi mai e lohe au i ka hauoli a me ka olioli; I hauoli hoi na iwi au i uhaki mai ai.
9 Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.
E huna oe i kou maka i ko'u mau lawehala ana, A e hoopau i ko'u mau hewa a pau.
10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run, kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
E haawi mai i naau maemae no'u, e ke Akua; E hana hou mai hoi i uhane kupono iloko o'u.
11 Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ, kí o má ṣe gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
Mai kiola ae oe ia'u mai kou alo ae; Aole hoi e lawe aku i kou Uhane Hemolele mai o'u aku nei.
12 Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá, kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.
E hoihoi mai ia'u i ka hauoli no kou ola; A e kokua mai ia'u me kou Uhane lokomaikai.
13 Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ, àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
Alaila, e ao aku au i na lawehala i kou mau aoao; A e hoohuliia na kanaka hewa ia oe.
14 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi, ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
E hoopakele ae ia'u i na koko, e ke Akua, e ko'u Akua e ola'i; A e himeni leo nui aku au i kou pono.
15 Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo, àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
E ka Haku, e wehe mai oe i ko'u lebelehe; A e hoike aku ko'u waha i kou hoolea.
16 Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá; Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
No ka mea, aole oe i makemake i ka alana; Alaila, e haawi aku no wau ia; Aole oe i oluolu mai i na mohaikuni.
17 Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.
O na mohai no ke Akua oia ka uhane mihi: O ka naau mihi me ka pepe, o kau ia, e ke Akua e hoowahawaha ole ai.
18 Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni, ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
E hana maikai mai oe ia Ziona i kou lokomaikai: E kukulu hoi oe i na pa o Ierusalema.
19 Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo, pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun, nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.
Alaila, e oluolu mai oe i na mohai o ka pono, I na mohaikuni, na mohaikuni okoa hoi; Alaila e kaumaha aku lakou i na bipi maluna o kou kuahu.