< Psalms 51 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nígbà ti wòlíì Natani tọ wá, lẹ́yìn tí Dafidi dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè rẹ̀ pẹ̀lú Batṣeba. Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ̀ kí o sì pa gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi rẹ́.
Thaburi ya Daudi Wee Ngai-rĩ, njiguĩra tha, kũringana na wendo waku ũrĩa ũtathiraga; kũringana na tha ciaku nyingĩ-rĩ, tharia mahĩtia makwa mathire.
2 Wẹ gbogbo àìṣedéédéé mi nù kúrò kí o sì wẹ̀ mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi!
Thambia mahĩtia makwa mothe, na ũũtherie mehia makwa.
3 Nítorí mo mọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi, nígbà gbogbo ni ẹ̀ṣẹ̀ mi wà níwájú mi.
Nĩgũkorwo nĩnjũũĩ mahĩtia makwa, namo mehia makwa makoragwo mbere yakwa hĩndĩ ciothe.
4 Sí ọ, ìwọ nìkan ṣoṣo, ni mo dẹ́ṣẹ̀ sí ni mo sì ṣe búburú níwájú rẹ̀, kí a lè dá ọ láre nígbà tí ìwọ bá ń sọ̀rọ̀, kí o sì le wà láìlẹ́bi, nígbà tí ìwọ bá ń ṣe ìdájọ́.
Wee nĩwe njĩhĩirie, o Wee wiki, na ngeeka ũndũ mũũru maitho-inĩ maku, nĩguo Wee wonekage ũtarĩ na mahĩtia rĩrĩa ũkwaria, na ũrĩ wa kĩhooto rĩrĩa ũgũtua ciira.
5 Nítòótọ́, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni a ti bí mi, nínú ẹ̀ṣẹ̀ ni ìyá mí sì lóyún mi.
Ti-itherũ ndaciarirwo ndĩ mwĩhia; maitũ aagĩire nda ya kũnjiara arĩ o na mehia.
6 Nítòótọ́ ìwọ fẹ́ òtítọ́ ní inú; ìwọ kọ́ mi ní ọgbọ́n ní ìhà ìkọ̀kọ̀.
Ti-itherũ, Wee wendaga ũhoro wa ma kuuma ngoro thĩinĩ; nĩ ũndũ ũcio ũndutaga kũgĩa na ũũgĩ ngoro-inĩ yakwa.
7 Wẹ̀ mí pẹ̀lú ewé hísópù, èmi yóò sì mọ́; fọ̀ mí, èmi yóò sì funfun ju yìnyín lọ.
Theria na mũthobi, na nĩngũthera; thaambia, na nĩngwerũha gũkĩra ira.
8 Jẹ́ kí n gbọ́ ayọ̀ àti inú dídùn; jẹ́ kí gbogbo egungun tí ìwọ ti run kí ó máa yọ̀.
Tũma ngene na njanjamũke; mahĩndĩ marĩa ũthetherete nĩmagĩkene.
9 Pa ojú rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi kí o sì pa gbogbo àwọn àìṣedéédéé mi rẹ́.
Hitha ũthiũ waku ndũkoone mehia makwa, na ũtharie mahĩtia makwa mothe.
10 Dá ọkàn mímọ́ sí inú mi, Ọlọ́run, kí o sì tún ẹ̀mí dídúró ṣinṣin ṣe sínú mi.
Wee Ngai-rĩ, nyũmbĩra ngoro theru thĩinĩ wakwa, na ũnjerũhĩrie roho wa kwĩhokeka thĩinĩ wakwa.
11 Má ṣe jù mi nù kúrò níwájú rẹ, kí o má ṣe gba Ẹ̀mí Mímọ́ rẹ lọ́wọ́ mi.
Ndũkanyingate nyume harĩwe, o na kana weherie Roho waku Mũtheru kuuma thĩinĩ wakwa.
12 Mú ayọ̀ ìgbàlà rẹ tọ̀ mí wá, kí o sì fún mi ní ẹ̀mí ìfẹ́, tí yóò mú mi dúró.
Njookeria gĩkeno kĩrĩa kĩa ũhonokio waku, na ũũhe roho wa kũndũũria ngwathĩkagĩra.
13 Nígbà náà ni èmi yóò máa kọ́ àwọn olùrékọjá ní ọ̀nà rẹ, àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ yóò sì yí padà sí ọ.
Hĩndĩ ĩyo nĩngaruta andũ arĩa aremi nĩguo mamenye njĩra ciaku, nao ehia magũcookerere.
14 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀, Ọlọ́run, ìwọ Ọlọ́run ìgbàlà mi, ahọ́n mi yóò sì máa kọrin òdodo rẹ kíkan.
Wee Ngai, o Wee Ngai ũrĩa ũũhonokagia-rĩ, honokia kuumana na ũiti thakame, naruo rũrĩmĩ rwakwa nĩrũkaina ũhoro wa ũthingu waku.
15 Olúwa, ṣí mi ní ètè mi gbogbo, àti ẹnu mi yóò sì máa kéde ìyìn rẹ.
Wee Mwathani, tumũra mĩromo yakwa, nako kanua gakwa koimbũre ũgooci waku.
16 Nítorí ìwọ kò ní inú dídùn sí ẹbọ, tí èmi kò bá mú wá; Ìwọ kò ní inú dídùn sí ọrẹ ẹbọ sísun.
Wee ndũkenagio nĩ kũrutĩrwo igongona, korwo nĩũkenagio nĩrĩo no ngũrutĩre; o na ndũkenagio nĩ magongona ma njino.
17 Ẹbọ Ọlọ́run ni ìròbìnújẹ́ ọkàn ìròbìnújẹ́ àti ìrora àyà.
Magongona marĩa Ngai etĩkagĩra nĩ roho ũrĩa mũthuthĩku; ngoro ĩrĩa thuthĩku na ĩkahera-rĩ, Wee Ngai ndũngĩmĩrega.
18 Ṣe rere ní dídùn inú rẹ sí Sioni, ṣe rere; tún odi Jerusalẹmu mọ.
Tũma itũũra rĩa Zayuni rĩgaacĩre nĩ ũndũ wa wega waku; aka thingo cia Jerusalemu rĩngĩ.
19 Nígbà náà ni inú rẹ yóò dùn sí ẹbọ òdodo, pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ọrẹ ẹbọ sísun, nígbà náà ni wọn yóò fi akọ màlúù rú ẹbọ lórí pẹpẹ rẹ.
Hĩndĩ ĩyo nĩũgakenagĩra magongona ma ũthingu, na maruta ma njino o marĩa macinagwo magathira biũ; ningĩ magongona ma ndegwa nĩmakarutagĩrwo kĩgongona-inĩ gĩaku.

< Psalms 51 >