< Psalms 50 >

1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
Asaf dwom. Tweaduampɔn, Onyankopɔn, Awurade no kasa, na ɔfrɛ asase nyinaa ɛfiri apueeɛ kɔsi atɔeɛ.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
Onyankopɔn hran firi Sion kuro a ne fɛ wie pɛ yɛ.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
Yɛn Onyankopɔn reba nanso ɔrenyɛ komm; ogya a ɛhye nneɛma di nʼanim, ahum a ɛretu atwa ne ho ahyia.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ɔfrɛ ɔsorosoro ne asase, sɛ ɔrebu ne nkurɔfoɔ atɛn;
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
Ɔka sɛ, “Boaboa nnipa a wɔate wɔn ho no ano ma me, wɔn a wɔnam afɔrebɔdeɛ so ne me yɛɛ apam no.”
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
Ɔsoro pae mu ka ne tenenee, na Onyankopɔn ankasa ne ɔtemmufoɔ.
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
“Montie, me nkurɔfoɔ na mɛkasa, mɛdi adanseɛ atia wo, Ao Israel; Mene Onyankopɔn, wo Onyankopɔn no.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
Merenka mo anim wɔ mo afɔrebɔdeɛ anaa mo hyeɛ afɔdeɛ a ɛwɔ mʼanim daa no ho.
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
Anantwinini a wɔfiri mo mfuo so anaa mpapo a wɔfiri mo buo mu ho nhia me,
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
ɛfiri sɛ kwaeɛ mu aboa biara yɛ me dea, anantwie a wɔwɔ nkokoɔ mpempem so nso saa ara.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
Menim anomaa biara a ɔwɔ mmepɔ no so, na wiram abɔdeɛ nyinaa yɛ me dea.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
Sɛ ɛkɔm dee me a, anka merenka nkyerɛ mo; ɛfiri sɛ, ewiase ne deɛ ɛwɔ mu nyinaa yɛ me dea.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
Mewe anantwinini nam, na menom mpapo mogya anaa?
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
Momfa aseda afɔdeɛ mma Onyankopɔn, na monni bɔhyɛ a mohyɛɛ Ɔsorosoroni no so,
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
na momfrɛ me da hiada; na mɛgye mo na moahyɛ me animuonyam.”
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
Nanso, amumuyɛfoɔ deɛ, Onyankopɔn bisa wɔn sɛ, “Adɛn enti na moka me mmara ho asɛm na mʼapam da mo ano?
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
Mokyiri me nkyerɛkyerɛ na moto me nsɛm gu mo akyi.
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
Sɛ mohunu ɔkorɔmfoɔ a, mode mo ho bɔ no; na mo ne awaresɛefoɔ nso bɔ.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
Mode mo ano yɛ bɔne na mode mo tɛkrɛma boaboa nnaadaa ano.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
Mokasa tia mo nuabarima ɛberɛ biara na mosopa mo ankasa maame ba.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
Moayɛ yeinom nyinaa; nanso manka hwee, enti mosusu sɛ mete sɛ mo. Nanso mɛka mo anim na mede mo soboɔ asi mo anim.
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
“Monnwene yei ho, mo a mo werɛ firi Onyankopɔn, anyɛ saa a, mɛtete mo mu nketenkete a obiara mmɛgye mo;
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
Deɛ ɔbɔ aseda afɔdeɛ no hyɛ me animuonyam, na ɔsiesie ɛkwan sɛdeɛ mɛda Onyankopɔn nkwagyeɛ adi akyerɛ no.” Wɔde ma dwomkyerɛfoɔ.

< Psalms 50 >