< Psalms 50 >

1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
مزمور آساف. یهوه، خدای خدایان، سخن می‌گوید؛ او همهٔ مردم را از مشرق تا مغرب نزد خود فرا می‌خواند.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
نور جلال خدا از کوه صهیون، که مظهر زیبایی و بزرگی اوست، می‌تابد.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
خدای ما خواهد آمد و سکوت نخواهد کرد. شعله‌های آتش در پیشاپیش او و گردباد در اطراف اوست.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
او آسمان و زمین را به گواهی می‌طلبد تا بر قوم خود داوری کند.
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
خداوند می‌فرماید: «قوم خاص مرا که با قربانیهای خود با من عهد بسته‌اند که نسبت به من وفادار بمانند، نزد من جمع کنید.»
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
آسمانها گواهند که خدا، خود داور است و با عدالت داوری می‌کند.
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
«ای قوم من، ای اسرائیل، به سخنان من گوش دهید، زیرا من خدای شما هستم! من خود بر ضد شما شهادت می‌دهم.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
دربارهٔ قربانی‌هایتان شما را سرزنش نمی‌کنم، زیرا قربانی‌های سوختنی خود را پیوسته به من تقدیم می‌کنید.
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
من محتاج گوساله‌ای از طویلۀ تو نیستم و نه بزی از آغُلت،
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
زیرا همهٔ حیواناتی که در جنگل و کوه هستند از آن منند.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
همهٔ پرندگانی که بر کوهها پرواز می‌کنند و تمام حیواناتی که در صحراها می‌چرند، به من تعلق دارند.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
اگر گرسنه هم می‌بودم از تو خوراک نمی‌خواستم، زیرا که جهان و هر چه که در آن است از آن من است.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
مگر من گوشت گاوها را می‌خورم و یا خون بزها را می‌نوشم؟
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
«قربانی واقعی که باید تقدیم کنید این است که خدای متعال را شکر نمایید و نذرهایی را که کرده‌اید ادا کنید.
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
هنگامی که در مشکلات هستید مرا بخوانید؛ من شما را نجات خواهم داد و شما مرا ستایش خواهید کرد.»
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
اما خدا به شریران چنین می‌گوید: «شما چه حق دارید که فرایض مرا بر زبان بیاورید و دربارهٔ عهد من سخن بگویید؟
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
زیرا شما از اصلاح شدن نفرت دارید و کلام مرا پشت گوش می‌اندازید.
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
وقتی دزد را می‌بینید که دزدی می‌کند با وی همدست می‌شوید و با زناکاران معاشرت می‌کنید.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
سخنان شما با خباثت و نیرنگ آمیخته است.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
هر جا می‌نشینید از برادرتان بد می‌گویید و غیبت می‌کنید.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
این کارها را کردید و من چیزی نگفتم. فکر کردید من هم مانند شما هستم! اما اینک من شما را برای تمام این کارها تنبیه می‌کنم.
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
«ای کسانی که مرا فراموش کرده‌اید، به من گوش دهید و گرنه شما را هلاک خواهم کرد و فریادرسی نخواهید داشت.
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
قربانی شایستهٔ من آنست که از من سپاسگزار باشید و مرا ستایش کنید. هر که چنین کند راه نجات را به او نشان خواهم داد.»

< Psalms 50 >