< Psalms 50 >

1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
مزمور آساف خدا، خدا یهوه تکلم می‌کند و زمین رااز مطلع آفتاب تا به مغربش می‌خواند.۱
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
از صهیون که کمال زیبایی است، خدا تجلی نموده است.۲
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
خدای ما می‌آید و سکوت نخواهد نمود. آتش پیش روی او می‌بلعد. وطوفان شدید گرداگرد وی خواهد بود.۳
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
آسمان را از بالا می‌خواند و زمین را، تا قوم خود راداوری کند:۴
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
«مقدسان مرا نزد من جمع کنید، که عهد را با من به قربانی بسته‌اند.»۵
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
و آسمانها ازانصاف او خبر خواهند داد. زیرا خدا خود داوراست، سلاه.۶
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
«ای قوم من بشنوتا سخن گویم. و‌ای اسرائیل تا برایت شهادت دهم که خدا، خدای تومن هستم.۷
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
درباره قربانی هایت تو را توبیخ نمی کنم و قربانی های سوختنی تو دائم در نظرمن است.۸
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
گوساله‌ای از خانه تو نمی گیرم و نه بزی از آغل تو.۹
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
زیراکه جمیع حیوانات جنگل از آن منند و بهایمی که بر هزاران کوه می‌باشند.۱۰
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
همه پرندگان کوهها را می‌شناسم و وحوش صحرا نزد من حاضرند.۱۱
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
اگر گرسنه می‌بودم تورا خبر نمی دادم. زیرا ربع مسکون و پری آن از آن من است.۱۲
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
آیا گوشت گاوان را بخورم و خون بزها را بنوشم؟۱۳
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
برای خدا قربانی تشکر رابگذران، و نذرهای خویش را به حضرت اعلی وفانما.۱۴
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
پس در روز تنگی مرا بخوان تا تو راخلاصی دهم و مرا تمجید بنمایی.»۱۵
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
و اما به شریر خدا می‌گوید: «ترا چه‌کاراست که فرایض مرا بیان کنی و عهد مرا به زبان خود بیاوری؟۱۶
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
چونکه تو از تادیب نفرت داشته‌ای و کلام مرا پشت سر خود انداخته‌ای.۱۷
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
چون دزد را دیدی او را پسند کردی و نصیب تو با زناکاران است.۱۸
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
دهان خود را به شرارت گشوده‌ای و زبانت حیله را اختراع می‌کند.۱۹
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
نشسته‌ای تا به ضد برادر خود سخن رانی ودرباره پسر مادر خویش غیبت‌گویی.۲۰
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
این راکردی و من سکوت نمودم. پس گمان بردی که من مثل تو هستم. لیکن تو را توبیخ خواهم کرد. و این را پیش نظر تو به ترتیب خواهم نهاد.۲۱
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
‌ای فراموش کنندگان خدا، در این تفکر کنید! مباداشما را بدرم و رهاننده‌ای نباشد.۲۲
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
هر‌که قربانی تشکر را گذراند مرا تمجید می‌کند. و آنکه طریق خود را راست سازد، نجات خدا را به وی نشان خواهم داد.»۲۳

< Psalms 50 >