< Psalms 50 >

1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
[Psalm lal Asaph] LEUM GOD, God Kulana, El kaskas; El pangon faclu nufon, mutawauk kutulap na nwe roto.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
Kalem lun God saromrom Zion me, Siti se su oaskulana in woiya.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
God lasr El tuku, tuh El tia tuku misla; Sie e lulap fah fahsr meet lukel, Ac sie eng upa raunella.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
El pangon kusrao ac faclu elos in orek loh kac, Ac liye ke El ac nununku mwet lal.
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
El fahk ouinge, “Eisani mwet oaru luk nu yuruk, Elos su tuh orek wulela yuruk ke mwe kisa.”
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
Kusrao fahkak lah God El suwoswos, Ac El sifacna pa Mwet Nununku.
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
“Porongo, kowos mwet luk, ac nga ac fah kaskas; Nga fah kaskas lain kom, Israel. Tuh nga God, God lom.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
Ke nga kai kom, tia ma ke sripen mwe kisa lom Ku ke mwe kisa firir su kom use nu sik pacl e nukewa.
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
Tusruktu nga tia enenu cow mukul liki ima lom, Ku nani liki un kosro nutum.
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
Kosro nukewa insak uh ma nutik, Ac oayapa cow su muta fin tausin inging.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
Won lemnak nukewa ma nutik Ac ma moul nukewa in imae.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
“Nga fin masrinsral, nga ac tia siyuk sum ke mwe mongo, Mweyen faclu ac koano nufon ma luk.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
Ya nga kang ikwen cow mukul uh, Ku nim srahn nani uh?
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
Nga God Fulatlana! Pa inge mwe kisa ma nga enenu sum: In sang kulo ke insiom, ac in akfalye ma kom wulela kac.
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
Pre nu sik ke pacl mwe ongoiya sikyak; Nga ac fah molikomla, Ac kom fah kaksakinyu.”
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
A God El fahk nu sin mwet koluk, “Efu ku kom in fahkak ma sap luk? Efu ku kom in sramsram ke wulela luk?
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
Kom tia lungse nga in aksuwosye kom; Kom pilesru ma sap luk.
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
Kom asruoki nu sin mwet pisrapasr nukewa kom liye, Ac kom insese yurin mukul ac mutan su tia karinganang wulela in marut la.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
“Pacl nukewa kom akola in kaskas koluk, Ac kom tia tupwek in kaskas kikiap.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
Kom akola in akkolukye mwet lom sifacna, Ac suk mwatan mwet lim.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
Kom oru ma inge nukewa, ac nga tia fahk kutena ma, Pwanang kom nunku mu nga oana kom. Tusruktu inge nga kai kom kac Tuh in kalem sum.
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
“Porongo ma inge, kowos su pilesreyu. Kowos fin tia, nga fah kunauskowosla, Na wangin sie ac fah molikowosla.
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
Sang kulo pa mwe kisa se ma akfulatyeyu, Ac nga fah molelosla nukewa su akosyu.”

< Psalms 50 >