< Psalms 50 >

1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
Thaburi ya Asafu Jehova, o we Ngai ũcio Mwene-Hinya, nĩaraaria, ageeta thĩ yothe kuuma irathĩro rĩa riũa nginya kũrĩa rĩthũagĩra.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
Ngai aracangarara arĩ Zayuni itũũra rĩu ithaka mũno.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
Ngai witũ nĩ gũũka arooka na ndegũkira; mbere yake nĩ mwaki ũrakana, na akarigiicĩrio nĩ kĩhuhũkanio kĩnene.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
Areeta igũrũ na thĩ nĩguo ituĩke aira agĩciirithia andũ ake:
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
“Cookanĩrĩrai harĩ niĩ inyuĩ andũ akwa aamũre, o inyuĩ mwagĩire kĩrĩkanĩro na niĩ na ũndũ wa kũndutĩra igongona.”
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
Narĩo igũrũ rĩanagĩrĩra ũthingu wake, nĩgũkorwo Ngai we mwene nĩwe mũtuanĩri ciira.
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
“Inyuĩ andũ akwa, thikĩrĩriai na nĩngwaria, ũthikĩrĩrie, wee Isiraeli, na nĩngũruta ũira wa gũgũthita: nĩ niĩ Ngai, o Ngai waku.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
Ndirakũrũithia nĩ ũndũ wa magongona maku, o na kana nĩ ũndũ wa maruta maku ma njino, marĩa makoragwo mbere yakwa hĩndĩ ciothe.
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
Ndibatarĩtio nĩ ndegwa yumĩte kiugũ gĩaku, kana mbũri ciumĩte ciugũ ciaku,
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
nĩgũkorwo nyamũ ciothe cia gĩthaka nĩ ciakwa, na ngʼombe iria irĩ tũrĩma-inĩ ngiri na ngiri.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
Nyoni ciothe iria irĩ kũu irĩma-inĩ, gũtirĩ o na ĩmwe itooĩ, na ciũmbe ciothe cia werũ-inĩ nĩ ciakwa.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
Ingĩkorwo hũtiĩ, ndingĩkwĩra, nĩgũkorwo thĩ nĩ yakwa, na kĩrĩa gĩothe kĩrĩ thĩinĩ wayo.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
Niĩ nĩndĩĩaga nyama cia ndegwa, o na kana nganyua thakame ya mbũri?
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
Rutĩra Ngai igongona rĩa gũcookia ngaatho, na ũhingagĩrie Ũrĩa-ũrĩ-Igũrũ-Mũno mĩĩhĩtwa yaku,
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
na ũngayagĩre mũthenya wa mĩnyamaro; na nĩndĩrĩkũhonokagia, nawe ũngoocage.”
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
No rĩrĩ, mũndũ ũrĩa mwaganu Ngai ekũmũũria atĩrĩ: “Ũrĩ na kĩhooto kĩrĩkũ gĩa kuuga mawatho makwa, kana kwaria ũhoro wa kĩrĩkanĩro gĩakwa?
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
Nĩũmenete ũrutani wakwa, na ũgateanĩria ciugo ciakwa.
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
Rĩrĩa wona mũici, ũnyiitanagĩra nake; na ũgĩĩaga ũrũmwe na itharia.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
Ũhũthagĩra kanua gaku kwaria ndeto njũru, na rũrĩmĩ rwaku naruo rũkaaragia maheeni.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
Hĩndĩ ciothe waragia ndeto cia gũũkĩrĩra mũrũ wa thoguo, ũgagĩcambia mũrũ-wa-nyũkwa.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
Maũndũ macio ũmekaga o ngirĩte, nawe ũgeciiria atĩ niĩ ndariĩ o tawe. No rĩrĩ, rĩu nĩngũkũrũithia, nguonie maũndũ marĩa wĩkĩte.
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
“Mwĩcũraniei ũhoro ũyũ, inyuĩ mũriganagĩrwo nĩ Ngai, nĩguo ndikamũtambuure, na haage mũndũ wa kũmũteithũra.
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
Mũndũ ũrĩa ũrutaga igongona rĩa gũcookia ngaatho nĩ niĩ atĩĩaga, na akahaarĩria njĩra nĩgeetha ndĩmuonie ũhonokanio wa Ngai.”

< Psalms 50 >