< Psalms 50 >
1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
Psaume d'Asaph. Le Dieu fort, Dieu, l'Éternel, a parlé: il a convoqué la terre, Du soleil levant au soleil couchant.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
De Sion, parfaite en beauté, Dieu fait rayonner sa splendeur.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
Il vient, notre Dieu, et il ne se tait point; Devant lui est un feu dévorant. Autour de lui une tempête furieuse.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
Il convoque les cieux d'en haut. Ainsi que la terre, pour juger son peuple:
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
«Rassemblez-moi mes fidèles, Qui ont scellé leur alliance avec moi par un sacrifice»
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
Et les cieux proclament sa justice; Car c'est Dieu lui-même qui va juger! (Pause)
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
Écoute, ô mon peuple, et je parlerai. Écoute, ô Israël! Je te ferai entendre mes avertissements: Je suis Dieu, ton Dieu.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
Ce n'est pas pour tes sacrifices que je te ferai des reproches, Ni pour tes holocaustes, qui sont continuellement devant moi.
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
Je ne prendrai point de taureau dans ta maison, Ni de bouc dans tes bergeries;
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
Car c'est à moi qu'appartiennent tous les animaux des forêts. Ainsi que les bêtes des montagnes, par milliers.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
Je connais tous les oiseaux des montagnes, Et tout ce qui se meut dans les champs m'appartient.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
Si j'avais faim, je ne t'en dirais rien; Car à moi est le monde et tout ce qu'il renferme.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
Ai-je besoin de manger la chair des taureaux, Ou de boire le sang des boucs?
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
Pour sacrifice, offre à Dieu tes louanges, Et accomplis tes voeux envers le Très-Haut!
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
Puis, invoque-moi au jour de la détresse: Je te délivrerai, et tu me glorifieras.
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
Mais Dieu dit au méchant: «A quoi bon réciter mes commandements Et célébrer des lèvres mon alliance,
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
Quand tu hais la réprimande Et quand tu repousses mes paroles loin de toi?
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
Lorsque tu vois un voleur, tu te plais avec lui; Tu fais cause commune avec les adultères.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
Tu livres ta bouche à la calomnie, Et ta langue ourdit la fraude.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
Tu t'assieds et tu parles contre ton frère; Tu diffames le fils de ta mère.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
Voilà ce que tu as fait; et parce que j'ai gardé le silence, Tu t'es imaginé que j'étais pareil à toi! Je vais te reprendre et mettre ton iniquité sous tes yeux.»
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
Comprenez donc cela, vous qui oubliez Dieu, De peur que je ne vous mette en pièces. Sans que personne puisse vous délivrer!
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
Celui qui offre pour sacrifice la louange, me glorifie; Et à celui qui veille sur sa conduite Je ferai contempler le salut de Dieu.