< Psalms 50 >
1 Saamu ti Asafu. Olúwa, Ọlọ́run alágbára, sọ̀rọ̀ kí o sì pe ayé jọ láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀ rẹ̀.
Асафов псалом. Господ Бог Иеова е говорил и призовал земята От изгряването на слънцето до захождането му.
2 Láti Sioni wá, pípé ni ẹwà, Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀
От Сион, съвършенството на красотата, Бог е възсиял.
3 Ọlọ́run ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́, iná yóò máa jó níwájú rẹ̀, àti ní àyíká rẹ̀ ni ẹ̀fúùfù líle yóò ti máa jà ká.
Нашият Бог ще дойде и няма да мълчи; Ще има пред Него огън поглъщащ, И около Него силна буря.
4 Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé, kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ще призове небесата отгоре, И земята, за да съди людете Си, казвайки:
5 “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún mi àwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi.”
Съберете Ми Моите светии, Които направиха с Мене завет с жертви.
6 Àwọn ọ̀run yóò sì sọ̀rọ̀ òdodo rẹ̀, nítorí Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni onídàájọ́.
И небесата ще известят правдата Му, Защото сам Бог е съдия. (Села)
7 “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Israẹli, èmi yóò jẹ́rìí sí ọ: èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run rẹ.
Слушайте, люде Мои, и ще говоря, - Израилю, и ще заявя пред тебе: Бог, твоят Бог съм Аз.
8 Èmi kí yóò bá ọ wí nítorí àwọn ìrúbọ rẹ, tàbí ọrẹ ẹbọ sísun rẹ, èyí tí ó wà níwájú mi ní ìgbà gbogbo.
Не ще да те изоблича поради жертвите ти, Нито поради твоите всеизгаряния, които са винаги пред Мене,
9 Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí o kọ́ fún un, tàbí kí o mú òbúkọ láti inú agbo ẹran rẹ̀
Не ща да приема юнец от къщата ти, Нито козли от стадата ти;
10 nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmi àti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.
Защото Мои са всичките горски зверове, И добитъкът, който е по хиляди хълмове.
11 Èmi mọ gbogbo ẹyẹ ní orí àwọn òkè ńlá àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó wà ní orí ilẹ̀ ni tèmi.
Познавам всичките планински птици, И полските зверове са в ума Ми.
12 Bí ebi tilẹ̀ ń pa mí, èmi kì yóò sọ fún ọ, nítorí ayé ni tèmi àti ohun gbogbo tí ó wa ní inú rẹ̀.
Ако огладнеех, не щях да кажа на тебе; Защото Моя е вселената и всичко що има в нея.
13 Ǹjẹ́ èmi yóò ha jẹ ẹran akọ màlúù tàbí mú ẹ̀jẹ̀ òbúkọ?
Ще ям ли Аз месо от юнци? Ще пия ли кръв от козли?
14 “Rú ẹbọ ọpẹ́ sí Ọlọ́run, kí o sì san ẹ̀jẹ́ rẹ fún Ọ̀gá-ògo.
Принеси Богу жертва на хваление, И изпълни на Всевишния обреците си;
15 Kí o sì pè mí ní ọjọ́ ìpọ́njú, èmi yóò gbà ọ́, ìwọ yóò sì bu ọlá fún mi.”
И призови Ме в ден на напаст; И Аз ще те избавя; и ти ще Ме прославиш.
16 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún àwọn, ènìyàn búburú: “Kí ní ẹ̀tọ́ tí o ní tí ìwọ fi ń tún àwọn ìlànà mi sọ, tàbí tí ìwọ sì ń sọ májẹ̀mú mi ní ẹnu rẹ?
Но на нечестивия казва Бог: Що правиш ти та разгласяваш Моите повеления, И разказваш завета Ми с устата си,
17 Ìwọ kórìíra àṣẹ mi, ìwọ sì ṣá ọ̀rọ̀ mí tì sí apá kan.
Тъй като сам ти мразиш поука, И хвърляш зад себе си Моите думи?
18 Nígbà tí ìwọ rí olè, ìwọ dára pọ̀ mọ́ ọn, ìwọ sì da ara rẹ dé àwọn alágbèrè.
Ако видиш крадец, тичаш с него, И с прелюбодейците участвуваш.
19 Ìwọ lo ẹnu rẹ fún aburú, ìwọ sì ń fi ahọ́n rẹ pète ẹ̀tàn.
Предаваш устата си на зло. И езикът ти устройва коварство.
20 Ní ìgbà gbogbo ìwọ ń sọ̀rọ̀ sí arákùnrin rẹ, ìwọ sì ń ba orúkọ ọmọ ìyá rẹ jẹ́.
Като седиш, говориш против брата си; Разсяваш клетвата против сина на майка си.
21 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ìwọ ti ṣe, mo sì dákẹ́; ìwọ rò pé mo jẹ́ irú kan náà bí ìrẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò bá ọ wí, èmi yóò sì fi ẹ̀sùn kàn ọ́ ní ojú ara rẹ.
Понеже си сторил това, и Аз премълчах, Ти си помислил, че съм съвсем подобен на тебе; Но Аз ще те изоблича, и ще изредя всичко това пред очите ти.
22 “Ǹjẹ́ ìwọ ro èyí wò, ẹ̀yin tí ó gbàgbé Ọlọ́run. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ èmi yóò fa yin ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, láìsí ẹni tí yóò gbà yin sílẹ̀.
Разсъдете, прочее, за това, вие, които забравяте Бога, Да не би да ви разкъсам, без да се намери кой да ви избави.
23 Ẹni tí ó ba ní ẹbọ ọrẹ-ọpẹ́ bu ọlá fún mi; kí ó sì tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe, kí èmi kí ó le fi ìgbàlà Ọlọ́run hàn án.”
Който принася жертва на хвала, той Ме прославя; И на онзи, който оправя пътя си, ще покажа Божието спасение.