< Psalms 5 >

1 Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi. Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa, kíyèsi àròyé mi.
Au maître-chantre. — Avec les flûtes. Psaume de David. Prête l'oreille à mes paroles, ô Éternel; Sois attentif à mes soupirs!
2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́, ọba mi àti Ọlọ́run mi, nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.
Écoute ma voix qui t'implore, ô mon Roi et mon Dieu; Car c'est à toi que s'adresse ma prière.
3 Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi; ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀ èmi yóò sì dúró ní ìrètí.
Éternel, dès le matin daigne entendre ma voix; Dès le matin je t'offre ma requête, et j'attends!
4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú; bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.
Car tu n'es pas un Dieu qui prenne plaisir au mal: Le méchant ne peut séjourner chez toi.
5 Àwọn agbéraga kò le è dúró níwájú rẹ̀. Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;
Les orgueilleux ne subsistent pas devant tes yeux; Tu hais tous les ouvriers d'iniquité.
6 ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run. Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn ni Olúwa yóò kórìíra.
Tu feras périr ceux qui profèrent le mensonge. L'Éternel a horreur de l'homme de sang et de fraude.
7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀, èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀; ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.
Mais moi, par ta grande bonté, j'entrerai dans ta maison; Je me prosternerai dans ton sanctuaire, Avec la crainte qui t'est due.
8 Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ, nítorí àwọn ọ̀tá mi, mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.
Éternel, dirige-moi dans les sentiers de ta justice, A cause de ceux qui épient ma conduite. Aplanis la voie devant moi!
9 Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́; ọkàn wọn kún fún ìparun. Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀; pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.
Car il n'y a point de sincérité dans leur bouche; Leur coeur ne pense qu'à détruire; Leur gosier est un sépulcre ouvert; Leur langue est pleine de flatterie.
10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run! Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn. Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn, nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.
Châtie-les, ô Dieu! Qu'ils échouent dans leurs desseins! Repousse-les à cause de la multitude de leurs crimes; Car ils se sont révoltés contre toi.
11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀; jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí. Tan ààbò rẹ sórí wọn, àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.
Mais tous ceux qui se confient en toi se réjouiront; Ils pousseront des cris d'allégresse, à jamais. Tu étendras sur eux ta protection. Et ceux qui aiment ton nom Triompheront en toi!
12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo; ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.
C'est toi, ô Éternel, qui bénis le juste; Tu l'entoures de ta bienveillance comme d'un bouclier.

< Psalms 5 >